Add parallel Print Page Options

Jobu ráhùn sí Ọlọ́run

Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré Jobu sọ, ó sì wí pé:

(A)“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé,
    àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn,
    kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá;
    bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn;
    kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e;
    kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri,
    kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà:
    kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
Kí òru náà kí ó yàgàn;
    kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún,
    tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn;
    kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i,
    bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 Nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi,
    láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.

11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá,
    tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi,
    tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́;
    èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé
    tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé
    tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí:
    bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu,
    níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀,
    wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀,
    ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.

Jobu kígbe nínú ìrora rẹ̀

20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì,
    àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá,
    tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi,
    tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni
    tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún,
    tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi;
    ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí,
    àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi;
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”

Job Speaks

After this, Job opened his mouth and cursed the day of his birth.(A) He said:

“May the day of my birth perish,
    and the night that said, ‘A boy is conceived!’(B)
That day—may it turn to darkness;
    may God above not care about it;
    may no light shine on it.
May gloom and utter darkness(C) claim it once more;
    may a cloud settle over it;
    may blackness overwhelm it.
That night—may thick darkness(D) seize it;
    may it not be included among the days of the year
    nor be entered in any of the months.
May that night be barren;
    may no shout of joy(E) be heard in it.
May those who curse days[a] curse that day,(F)
    those who are ready to rouse Leviathan.(G)
May its morning stars become dark;
    may it wait for daylight in vain
    and not see the first rays of dawn,(H)
10 for it did not shut the doors of the womb on me
    to hide trouble from my eyes.

11 “Why did I not perish at birth,
    and die as I came from the womb?(I)
12 Why were there knees to receive me(J)
    and breasts that I might be nursed?
13 For now I would be lying down(K) in peace;
    I would be asleep and at rest(L)
14 with kings and rulers of the earth,(M)
    who built for themselves places now lying in ruins,(N)
15 with princes(O) who had gold,
    who filled their houses with silver.(P)
16 Or why was I not hidden away in the ground like a stillborn child,(Q)
    like an infant who never saw the light of day?(R)
17 There the wicked cease from turmoil,(S)
    and there the weary are at rest.(T)
18 Captives(U) also enjoy their ease;
    they no longer hear the slave driver’s(V) shout.(W)
19 The small and the great are there,(X)
    and the slaves are freed from their owners.

20 “Why is light given to those in misery,
    and life to the bitter of soul,(Y)
21 to those who long for death that does not come,(Z)
    who search for it more than for hidden treasure,(AA)
22 who are filled with gladness
    and rejoice when they reach the grave?(AB)
23 Why is life given to a man
    whose way is hidden,(AC)
    whom God has hedged in?(AD)
24 For sighing(AE) has become my daily food;(AF)
    my groans(AG) pour out like water.(AH)
25 What I feared has come upon me;
    what I dreaded(AI) has happened to me.(AJ)
26 I have no peace,(AK) no quietness;
    I have no rest,(AL) but only turmoil.”(AM)

Footnotes

  1. Job 3:8 Or curse the sea