Add parallel Print Page Options

Ọlọ́run kì í pọ́n ni lójú láìnídìí

37 “Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú,
    ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,
    àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo,
    Mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù;
    ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá.
Òhun kì yóò sì dá àrá dúró,
    nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu;
    ohùn ńláńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’
    àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀,
    ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ,
    wọn a sì wà ni ipò wọn.
Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá,
    àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni,
    ibú omi á sì súnkì.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo,
    a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
12 Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀,
    kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun
    tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
13 Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀,
    tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.

14 “Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí;
    dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
15 Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀,
    tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
16 Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ,
    iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
17 Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná,
    nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin,
    tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?

19 “Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un;
    nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀?
    Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
21 Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí
    oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀,
    ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
22 Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá;
    lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
23 Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá;
    nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀,
    òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”

37 “At this my heart pounds(A)
    and leaps from its place.
Listen!(B) Listen to the roar of his voice,(C)
    to the rumbling that comes from his mouth.(D)
He unleashes his lightning(E) beneath the whole heaven
    and sends it to the ends of the earth.(F)
After that comes the sound of his roar;
    he thunders(G) with his majestic voice.(H)
When his voice resounds,
    he holds nothing back.
God’s voice thunders(I) in marvelous ways;(J)
    he does great things beyond our understanding.(K)
He says to the snow,(L) ‘Fall on the earth,’
    and to the rain shower, ‘Be a mighty downpour.’(M)
So that everyone he has made may know his work,(N)
    he stops all people from their labor.[a](O)
The animals take cover;(P)
    they remain in their dens.(Q)
The tempest comes out from its chamber,(R)
    the cold from the driving winds.(S)
10 The breath of God produces ice,
    and the broad waters become frozen.(T)
11 He loads the clouds with moisture;(U)
    he scatters his lightning(V) through them.(W)
12 At his direction they swirl around
    over the face of the whole earth
    to do whatever he commands them.(X)
13 He brings the clouds to punish people,(Y)
    or to water his earth and show his love.(Z)

14 “Listen(AA) to this, Job;
    stop and consider God’s wonders.(AB)
15 Do you know how God controls the clouds
    and makes his lightning(AC) flash?(AD)
16 Do you know how the clouds hang poised,(AE)
    those wonders of him who has perfect knowledge?(AF)
17 You who swelter in your clothes
    when the land lies hushed under the south wind,(AG)
18 can you join him in spreading out the skies,(AH)
    hard as a mirror of cast bronze?(AI)

19 “Tell us what we should say to him;(AJ)
    we cannot draw up our case(AK) because of our darkness.(AL)
20 Should he be told that I want to speak?
    Would anyone ask to be swallowed up?
21 Now no one can look at the sun,(AM)
    bright as it is in the skies
    after the wind has swept them clean.
22 Out of the north he comes in golden splendor;(AN)
    God comes in awesome majesty.(AO)
23 The Almighty is beyond our reach and exalted in power;(AP)
    in his justice(AQ) and great righteousness, he does not oppress.(AR)
24 Therefore, people revere him,(AS)
    for does he not have regard for all the wise(AT) in heart?[b]

Footnotes

  1. Job 37:7 Or work, / he fills all people with fear by his power
  2. Job 37:24 Or for he does not have regard for any who think they are wise.