Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ Elifasi: Ọlọ́run kì í fi ìyà jẹ olódodo

Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé:

“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?
    Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,
    ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,
    ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;
    ara rẹ kò lélẹ̀.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ
    àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?
    Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,
    tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,
    nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún
    àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,
    àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.

12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,
    etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru,
    nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì
    tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,
    irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́,
    ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,
àwòrán kan hàn níwájú mi,
    ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,
    ènìyàn ha le mọ́ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,
    nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,
    ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀
    tí yóò di rírun kòkòrò.
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́
    wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?
    Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

Eliphaz

Then Eliphaz the Temanite(A) replied:

“If someone ventures a word with you, will you be impatient?
    But who can keep from speaking?(B)
Think how you have instructed many,(C)
    how you have strengthened feeble hands.(D)
Your words have supported those who stumbled;(E)
    you have strengthened faltering knees.(F)
But now trouble comes to you, and you are discouraged;(G)
    it strikes(H) you, and you are dismayed.(I)
Should not your piety be your confidence(J)
    and your blameless(K) ways your hope?

“Consider now: Who, being innocent, has ever perished?(L)
    Where were the upright ever destroyed?(M)
As I have observed,(N) those who plow evil(O)
    and those who sow trouble reap it.(P)
At the breath of God(Q) they perish;
    at the blast of his anger they are no more.(R)
10 The lions may roar(S) and growl,
    yet the teeth of the great lions(T) are broken.(U)
11 The lion perishes for lack of prey,(V)
    and the cubs of the lioness are scattered.(W)

12 “A word(X) was secretly brought to me,
    my ears caught a whisper(Y) of it.(Z)
13 Amid disquieting dreams in the night,
    when deep sleep falls on people,(AA)
14 fear and trembling(AB) seized me
    and made all my bones shake.(AC)
15 A spirit glided past my face,
    and the hair on my body stood on end.(AD)
16 It stopped,
    but I could not tell what it was.
A form stood before my eyes,
    and I heard a hushed voice:(AE)
17 ‘Can a mortal be more righteous than God?(AF)
    Can even a strong man be more pure than his Maker?(AG)
18 If God places no trust in his servants,(AH)
    if he charges his angels with error,(AI)
19 how much more those who live in houses of clay,(AJ)
    whose foundations(AK) are in the dust,(AL)
    who are crushed(AM) more readily than a moth!(AN)
20 Between dawn and dusk they are broken to pieces;
    unnoticed, they perish forever.(AO)
21 Are not the cords of their tent pulled up,(AP)
    so that they die(AQ) without wisdom?’(AR)