Add parallel Print Page Options

Ìsunjáde láti inú ara ti ń sọ ni di aláìmọ́

15 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé: Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀: kí ẹ wí fún wọn pé: Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara: ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́. Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́.

“ ‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́. Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀: kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

“ ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

“ ‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀: yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

“ ‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́. 10 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

11 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.

12 “ ‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.

13 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀: yóò sì di mímọ́. 14 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà. 15 Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.

16 “ ‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀: kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. 17 Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀: yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́. 18 Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀: kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

19 “ ‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀: obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.

20 “ ‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́. 21 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. 22 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. 23 Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

24 “ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.

25 “ ‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. 26 Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. 27 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.

28 “ ‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́. 29 Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. 30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.

31 “ ‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́: Èyí tí ó wà láàrín wọn.’ ”

32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀. 33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.

Discharges Causing Uncleanness

15 The Lord said to Moses and Aaron, “Speak to the Israelites and say to them: ‘When any man has an unusual bodily discharge,(A) such a discharge is unclean. Whether it continues flowing from his body or is blocked, it will make him unclean. This is how his discharge will bring about uncleanness:

“‘Any bed the man with a discharge lies on will be unclean, and anything he sits on will be unclean. Anyone who touches his bed must wash their clothes(B) and bathe with water,(C) and they will be unclean till evening.(D) Whoever sits on anything that the man with a discharge sat on must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

“‘Whoever touches the man(E) who has a discharge(F) must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

“‘If the man with the discharge spits(G) on anyone who is clean, they must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

“‘Everything the man sits on when riding will be unclean, 10 and whoever touches any of the things that were under him will be unclean till evening; whoever picks up those things(H) must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

11 “‘Anyone the man with a discharge touches without rinsing his hands with water must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

12 “‘A clay pot(I) that the man touches must be broken, and any wooden article(J) is to be rinsed with water.

13 “‘When a man is cleansed from his discharge, he is to count off seven days(K) for his ceremonial cleansing; he must wash his clothes and bathe himself with fresh water, and he will be clean.(L) 14 On the eighth day he must take two doves or two young pigeons(M) and come before the Lord to the entrance to the tent of meeting and give them to the priest. 15 The priest is to sacrifice them, the one for a sin offering[a](N) and the other for a burnt offering.(O) In this way he will make atonement before the Lord for the man because of his discharge.(P)

16 “‘When a man has an emission of semen,(Q) he must bathe his whole body with water, and he will be unclean till evening.(R) 17 Any clothing or leather that has semen on it must be washed with water, and it will be unclean till evening. 18 When a man has sexual relations with a woman and there is an emission of semen,(S) both of them must bathe with water, and they will be unclean till evening.

19 “‘When a woman has her regular flow of blood, the impurity of her monthly period(T) will last seven days, and anyone who touches her will be unclean till evening.

20 “‘Anything she lies on during her period will be unclean, and anything she sits on will be unclean. 21 Anyone who touches her bed will be unclean; they must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.(U) 22 Anyone who touches anything she sits on will be unclean; they must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening. 23 Whether it is the bed or anything she was sitting on, when anyone touches it, they will be unclean till evening.

24 “‘If a man has sexual relations with her and her monthly flow(V) touches him, he will be unclean for seven days; any bed he lies on will be unclean.

25 “‘When a woman has a discharge of blood for many days at a time other than her monthly period(W) or has a discharge that continues beyond her period, she will be unclean as long as she has the discharge, just as in the days of her period. 26 Any bed she lies on while her discharge continues will be unclean, as is her bed during her monthly period, and anything she sits on will be unclean, as during her period. 27 Anyone who touches them will be unclean; they must wash their clothes and bathe with water, and they will be unclean till evening.

28 “‘When she is cleansed from her discharge, she must count off seven days, and after that she will be ceremonially clean. 29 On the eighth day she must take two doves or two young pigeons(X) and bring them to the priest at the entrance to the tent of meeting. 30 The priest is to sacrifice one for a sin offering and the other for a burnt offering. In this way he will make atonement for her before the Lord for the uncleanness of her discharge.(Y)

31 “‘You must keep the Israelites separate from things that make them unclean, so they will not die in their uncleanness for defiling my dwelling place,[b](Z) which is among them.’”

32 These are the regulations for a man with a discharge, for anyone made unclean by an emission of semen,(AA) 33 for a woman in her monthly period, for a man or a woman with a discharge, and for a man who has sexual relations with a woman who is ceremonially unclean.(AB)

Footnotes

  1. Leviticus 15:15 Or purification offering; also in verse 30
  2. Leviticus 15:31 Or my tabernacle