Add parallel Print Page Options

Ìjìyà fún ẹ̀ṣẹ̀

20 Olúwa sọ fún Mose pé, (A)“Sọ fún àwọn ará Israẹli pé: ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa. Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú. Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀. Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn: òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.

(B)“ ‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn: Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀; Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.

(C)“ ‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́: Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.

(D)“ ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.

10 (E)“ ‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.

11 (F)“ ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.

12 (G)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.

13 (H)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra: pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.

14 (I)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀: ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.

15 (J)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.

16 “ ‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa: ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.

17 (K)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí: Ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn: ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.

18 (L)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.

19 (M)“ ‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ: Ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.

20 (N)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.

21 (O)“ ‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.

22 “ ‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde. 23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn. 24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn; Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.

25 “ ‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́. 26 (P)Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.

27 (Q)“ ‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’ ”

Punishments for Sin

20 The Lord said to Moses, “Say to the Israelites: ‘Any Israelite or any foreigner residing in Israel who sacrifices any of his children to Molek is to be put to death.(A) The members of the community are to stone him.(B) I myself will set my face against him and will cut him off from his people;(C) for by sacrificing his children to Molek, he has defiled(D) my sanctuary(E) and profaned my holy name.(F) If the members of the community close their eyes when that man sacrifices one of his children to Molek and if they fail to put him to death,(G) I myself will set my face against him and his family and will cut them off from their people together with all who follow him in prostituting themselves to Molek.

“‘I will set my face against anyone who turns to mediums and spiritists to prostitute themselves by following them, and I will cut them off from their people.(H)

“‘Consecrate yourselves(I) and be holy,(J) because I am the Lord your God.(K) Keep my decrees(L) and follow them. I am the Lord, who makes you holy.(M)

“‘Anyone who curses their father(N) or mother(O) is to be put to death.(P) Because they have cursed their father or mother, their blood will be on their own head.(Q)

10 “‘If a man commits adultery with another man’s wife(R)—with the wife of his neighbor—both the adulterer and the adulteress are to be put to death.(S)

11 “‘If a man has sexual relations with his father’s wife, he has dishonored his father.(T) Both the man and the woman are to be put to death; their blood will be on their own heads.(U)

12 “‘If a man has sexual relations with his daughter-in-law,(V) both of them are to be put to death. What they have done is a perversion; their blood will be on their own heads.

13 “‘If a man has sexual relations with a man as one does with a woman, both of them have done what is detestable.(W) They are to be put to death; their blood will be on their own heads.

14 “‘If a man marries both a woman and her mother,(X) it is wicked. Both he and they must be burned in the fire,(Y) so that no wickedness will be among you.(Z)

15 “‘If a man has sexual relations with an animal,(AA) he is to be put to death,(AB) and you must kill the animal.

16 “‘If a woman approaches an animal to have sexual relations with it, kill both the woman and the animal. They are to be put to death; their blood will be on their own heads.

17 “‘If a man marries his sister(AC), the daughter of either his father or his mother, and they have sexual relations, it is a disgrace. They are to be publicly removed(AD) from their people. He has dishonored his sister and will be held responsible.(AE)

18 “‘If a man has sexual relations with a woman during her monthly period,(AF) he has exposed the source of her flow, and she has also uncovered it. Both of them are to be cut off from their people.(AG)

19 “‘Do not have sexual relations with the sister of either your mother or your father,(AH) for that would dishonor a close relative; both of you would be held responsible.

20 “‘If a man has sexual relations with his aunt,(AI) he has dishonored his uncle. They will be held responsible; they will die childless.(AJ)

21 “‘If a man marries his brother’s wife,(AK) it is an act of impurity; he has dishonored his brother. They will be childless.(AL)

22 “‘Keep all my decrees and laws(AM) and follow them, so that the land(AN) where I am bringing you to live may not vomit you out. 23 You must not live according to the customs of the nations(AO) I am going to drive out before you.(AP) Because they did all these things, I abhorred them.(AQ) 24 But I said to you, “You will possess their land; I will give it to you as an inheritance, a land flowing with milk and honey.”(AR) I am the Lord your God, who has set you apart from the nations.(AS)

25 “‘You must therefore make a distinction between clean and unclean animals and between unclean and clean birds.(AT) Do not defile yourselves by any animal or bird or anything that moves along the ground—those that I have set apart as unclean for you. 26 You are to be holy to me(AU) because I, the Lord, am holy,(AV) and I have set you apart from the nations(AW) to be my own.

27 “‘A man or woman who is a medium(AX) or spiritist among you must be put to death.(AY) You are to stone them;(AZ) their blood will be on their own heads.’”