Add parallel Print Page Options

Ìkìlọ̀ fún àwọn àlùfáà

“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín. Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.

“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀. Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á. Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.

“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”

10 Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?

11 Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó. 12 Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

13 Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe: Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín. 14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.

15 Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.

16 “Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” Ṣe ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.

Ọjọ́ ìdájọ́

17 Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara.

Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?”

Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”

Additional Warning to the Priests

“And now, you priests, this warning is for you.(A) If you do not listen,(B) and if you do not resolve to honor(C) my name,” says the Lord Almighty, “I will send a curse(D) on you, and I will curse your blessings.(E) Yes, I have already cursed them, because you have not resolved to honor me.

“Because of you I will rebuke your descendants[a]; I will smear on your faces the dung(F) from your festival sacrifices, and you will be carried off with it.(G) And you will know that I have sent you this warning so that my covenant with Levi(H) may continue,” says the Lord Almighty. “My covenant was with him, a covenant(I) of life and peace,(J) and I gave them to him; this called for reverence(K) and he revered me and stood in awe of my name. True instruction(L) was in his mouth and nothing false was found on his lips. He walked(M) with me in peace(N) and uprightness,(O) and turned many from sin.(P)

“For the lips of a priest(Q) ought to preserve knowledge, because he is the messenger(R) of the Lord Almighty and people seek instruction from his mouth.(S) But you have turned from the way(T) and by your teaching have caused many to stumble;(U) you have violated the covenant(V) with Levi,”(W) says the Lord Almighty. “So I have caused you to be despised(X) and humiliated(Y) before all the people, because you have not followed my ways but have shown partiality(Z) in matters of the law.”(AA)

Breaking Covenant Through Divorce

10 Do we not all have one Father[b]?(AB) Did not one God create us?(AC) Why do we profane the covenant(AD) of our ancestors by being unfaithful(AE) to one another?

11 Judah has been unfaithful. A detestable(AF) thing has been committed in Israel and in Jerusalem: Judah has desecrated the sanctuary the Lord loves(AG) by marrying(AH) women who worship a foreign god.(AI) 12 As for the man who does this, whoever he may be, may the Lord remove(AJ) him from the tents of Jacob[c](AK)—even though he brings an offering(AL) to the Lord Almighty.

13 Another thing you do: You flood the Lord’s altar with tears.(AM) You weep and wail(AN) because he no longer looks with favor(AO) on your offerings or accepts them with pleasure from your hands.(AP) 14 You ask,(AQ) “Why?” It is because the Lord is the witness(AR) between you and the wife of your youth.(AS) You have been unfaithful to her, though she is your partner, the wife of your marriage covenant.(AT)

15 Has not the one God made you?(AU) You belong to him in body and spirit. And what does the one God seek? Godly offspring.[d](AV) So be on your guard,(AW) and do not be unfaithful(AX) to the wife of your youth.

16 “The man who hates and divorces his wife,(AY)” says the Lord, the God of Israel, “does violence to the one he should protect,”[e](AZ) says the Lord Almighty.

So be on your guard,(BA) and do not be unfaithful.

Breaking Covenant Through Injustice

17 You have wearied(BB) the Lord with your words.

“How have we wearied him?” you ask.(BC)

By saying, “All who do evil are good in the eyes of the Lord, and he is pleased(BD) with them” or “Where is the God of justice?(BE)

Footnotes

  1. Malachi 2:3 Or will blight your grain
  2. Malachi 2:10 Or father
  3. Malachi 2:12 Or 12 May the Lord remove from the tents of Jacob anyone who gives testimony in behalf of the man who does this
  4. Malachi 2:15 The meaning of the Hebrew for the first part of this verse is uncertain.
  5. Malachi 2:16 Or “I hate divorce,” says the Lord, the God of Israel, “because the man who divorces his wife covers his garment with violence,”