Mika 4
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Òkè Olúwa
4 (A)Ní ọjọ́ ìkẹyìn
a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,
a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá,
wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu
Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn,
yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré.
Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀
àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé
orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́,
bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
4 (B)Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀
àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀,
ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n,
nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn,
olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀,
ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa.
Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
Èrò Olúwa
6 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,
“Èmi yóò kó àwọn arọ jọ;
èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ,
àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù,
èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára.
Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni
láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn,
odi alágbára ọmọbìnrin Sioni,
a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín;
ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí?
Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí?
Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí?
Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
10 Máa yí síhìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora,
ìwọ obìnrin Sioni,
bí ẹni tí ń rọbí,
nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú,
ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó.
Ìwọ yóò lọ sí Babeli;
níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà.
Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́,
Ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ
èrò inú Olúwa;
Bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn,
nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin,
èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ
ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.”
Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa
àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
Micah 4
New International Version
The Mountain of the Lord(A)
4 In the last days
the mountain(B) of the Lord’s temple will be established
as the highest of the mountains;
it will be exalted above the hills,(C)
and peoples will stream to it.(D)
2 Many nations will come and say,
“Come, let us go up to the mountain of the Lord,(E)
to the temple of the God of Jacob.(F)
He will teach us(G) his ways,(H)
so that we may walk in his paths.”
The law(I) will go out from Zion,
the word of the Lord from Jerusalem.
3 He will judge between many peoples
and will settle disputes for strong nations far and wide.(J)
They will beat their swords into plowshares
and their spears into pruning hooks.(K)
Nation will not take up sword against nation,
nor will they train for war(L) anymore.(M)
4 Everyone will sit under their own vine
and under their own fig tree,(N)
and no one will make them afraid,(O)
for the Lord Almighty has spoken.(P)
5 All the nations may walk
in the name of their gods,(Q)
but we will walk in the name of the Lord
our God for ever and ever.(R)
The Lord’s Plan
6 “In that day,” declares the Lord,
“I will gather the lame;(S)
I will assemble the exiles(T)
and those I have brought to grief.(U)
7 I will make the lame my remnant,(V)
those driven away a strong nation.(W)
The Lord will rule over them in Mount Zion(X)
from that day and forever.(Y)
8 As for you, watchtower of the flock,
stronghold[a] of Daughter Zion,
the former dominion will be restored(Z) to you;
kingship will come to Daughter Jerusalem.(AA)”
9 Why do you now cry aloud—
have you no king[b](AB)?
Has your ruler[c] perished,
that pain seizes you like that of a woman in labor?(AC)
10 Writhe in agony, Daughter Zion,
like a woman in labor,
for now you must leave the city
to camp in the open field.
You will go to Babylon;(AD)
there you will be rescued.
There the Lord will redeem(AE) you
out of the hand of your enemies.
11 But now many nations
are gathered against you.
They say, “Let her be defiled,
let our eyes gloat(AF) over Zion!”
12 But they do not know
the thoughts of the Lord;
they do not understand his plan,(AG)
that he has gathered them like sheaves to the threshing floor.
13 “Rise and thresh,(AH) Daughter Zion,
for I will give you horns of iron;
I will give you hooves of bronze,
and you will break to pieces many nations.”(AI)
You will devote their ill-gotten gains to the Lord,(AJ)
their wealth to the Lord of all the earth.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.