Mika 5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu
5 Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,
ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,
nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.
Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.
2 “Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,
bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,
nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli
yóò ti jáde tọ̀ mí wá,
ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,
láti ìgbà láéláé.”
3 Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá
títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,
àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà
láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.
4 Òun yóò sì dúró,
yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,
ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Wọn yóò sì wà láìléwu,
nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ
yóò sì dé òpin ayé.
Ìgbàlà àti ìparun
5 Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.
Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa
tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,
nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,
àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.
6 Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,
àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.
Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria
nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa
tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.
7 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà
láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn
bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,
bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,
tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn
tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.
8 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà
ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,
bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,
bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,
èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,
tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.
9 A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.
10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,
“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ
èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.
11 Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,
èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.
12 Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,
ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.
13 Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,
àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;
ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀
fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.
14 Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,
èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.
15 Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú
lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”
Micah 5
New International Version
A Promised Ruler From Bethlehem
5 [a]Marshal your troops now, city of troops,
for a siege is laid against us.
They will strike Israel’s ruler
on the cheek(A) with a rod.
2 “But you, Bethlehem(B) Ephrathah,(C)
though you are small among the clans[b] of Judah,
out of you will come for me
one who will be ruler(D) over Israel,
whose origins are from of old,(E)
from ancient times.”(F)
3 Therefore Israel will be abandoned(G)
until the time when she who is in labor bears a son,
and the rest of his brothers return
to join the Israelites.
4 He will stand and shepherd his flock(H)
in the strength of the Lord,
in the majesty of the name of the Lord his God.
And they will live securely, for then his greatness(I)
will reach to the ends of the earth.
5 And he will be our peace(J)
when the Assyrians invade(K) our land
and march through our fortresses.
We will raise against them seven shepherds,
even eight commanders,(L)
6 who will rule[c] the land of Assyria with the sword,
the land of Nimrod(M) with drawn sword.[d](N)
He will deliver us from the Assyrians
when they invade our land
and march across our borders.(O)
7 The remnant(P) of Jacob will be
in the midst of many peoples
like dew(Q) from the Lord,
like showers on the grass,(R)
which do not wait for anyone
or depend on man.
8 The remnant of Jacob will be among the nations,
in the midst of many peoples,
like a lion among the beasts of the forest,(S)
like a young lion among flocks of sheep,
which mauls and mangles(T) as it goes,
and no one can rescue.(U)
9 Your hand will be lifted up(V) in triumph over your enemies,
and all your foes will be destroyed.
10 “In that day,” declares the Lord,
“I will destroy your horses from among you
and demolish your chariots.(W)
11 I will destroy the cities(X) of your land
and tear down all your strongholds.(Y)
12 I will destroy your witchcraft
and you will no longer cast spells.(Z)
13 I will destroy your idols(AA)
and your sacred stones from among you;(AB)
you will no longer bow down
to the work of your hands.(AC)
14 I will uproot from among you your Asherah poles[e](AD)
when I demolish your cities.
15 I will take vengeance(AE) in anger and wrath
on the nations that have not obeyed me.”
Footnotes
- Micah 5:1 In Hebrew texts 5:1 is numbered 4:14, and 5:2-15 is numbered 5:1-14.
- Micah 5:2 Or rulers
- Micah 5:6 Or crush
- Micah 5:6 Or Nimrod in its gates
- Micah 5:14 That is, wooden symbols of the goddess Asherah
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.