Add parallel Print Page Options

Àwọn ọrẹ àfikún

15 Olúwa sọ fún Mose pé; “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé: ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran, nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òṣùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa. Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òṣùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.

“ ‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òṣùwọ̀n òróró pò. Àti ìdákan nínú mẹ́ta òṣùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.

“ ‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa, Ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òṣùwọ̀n òróró pò. 10 Kí ó tún mú ìdajì òṣùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa. 11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́. 12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.

13 “ ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa. 14 (A)Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe. 15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa: 16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’ ”

17 (B)Olúwa sọ fún Mose pé, 18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ. 19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa. 20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín. 21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.

Ọrẹ fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀

22 (C)“ ‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́: 23 Èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀. 24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. 25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀. 26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.

27 (D)“ ‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. 28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í. 29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.

30 “ ‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀ 31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’ ”

Ìjìyà fún rírú òfin ọjọ́ ìsinmi

32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi. 33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn; 34 Wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn. 35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.” 36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

Wajawaja lára aṣọ

37 Olúwa sọ fún Mose pé, 38 (E)“Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan. 39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín. 40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín. 41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’ ”

Supplementary Offerings

15 The Lord said to Moses, “Speak to the Israelites and say to them: ‘After you enter the land I am giving you(A) as a home and you present to the Lord food offerings from the herd or the flock,(B) as an aroma pleasing to the Lord(C)—whether burnt offerings(D) or sacrifices, for special vows or freewill offerings(E) or festival offerings(F) then the person who brings an offering shall present to the Lord a grain offering(G) of a tenth of an ephah[a] of the finest flour(H) mixed with a quarter of a hin[b] of olive oil. With each lamb(I) for the burnt offering or the sacrifice, prepare a quarter of a hin of wine(J) as a drink offering.(K)

“‘With a ram(L) prepare a grain offering(M) of two-tenths of an ephah[c](N) of the finest flour mixed with a third of a hin[d] of olive oil,(O) and a third of a hin of wine(P) as a drink offering.(Q) Offer it as an aroma pleasing to the Lord.(R)

“‘When you prepare a young bull(S) as a burnt offering or sacrifice, for a special vow(T) or a fellowship offering(U) to the Lord, bring with the bull a grain offering(V) of three-tenths of an ephah[e](W) of the finest flour mixed with half a hin[f] of olive oil, 10 and also bring half a hin of wine(X) as a drink offering.(Y) This will be a food offering, an aroma pleasing to the Lord.(Z) 11 Each bull or ram, each lamb or young goat, is to be prepared in this manner. 12 Do this for each one, for as many as you prepare.(AA)

13 “‘Everyone who is native-born(AB) must do these things in this way when they present a food offering as an aroma pleasing to the Lord.(AC) 14 For the generations to come,(AD) whenever a foreigner(AE) or anyone else living among you presents a food(AF) offering(AG) as an aroma pleasing to the Lord, they must do exactly as you do. 15 The community is to have the same rules for you and for the foreigner residing among you; this is a lasting ordinance for the generations to come.(AH) You and the foreigner shall be the same before the Lord: 16 The same laws and regulations will apply both to you and to the foreigner residing among you.(AI)’”

17 The Lord said to Moses, 18 “Speak to the Israelites and say to them: ‘When you enter the land to which I am taking you(AJ) 19 and you eat the food of the land,(AK) present a portion as an offering to the Lord.(AL) 20 Present a loaf from the first of your ground meal(AM) and present it as an offering from the threshing floor.(AN) 21 Throughout the generations to come(AO) you are to give this offering to the Lord from the first of your ground meal.(AP)

Offerings for Unintentional Sins

22 “‘Now if you as a community unintentionally fail to keep any of these commands the Lord gave Moses(AQ) 23 any of the Lord’s commands to you through him, from the day the Lord gave them and continuing through the generations to come(AR) 24 and if this is done unintentionally(AS) without the community being aware of it,(AT) then the whole community is to offer a young bull for a burnt offering(AU) as an aroma pleasing to the Lord,(AV) along with its prescribed grain offering(AW) and drink offering,(AX) and a male goat for a sin offering.[g](AY) 25 The priest is to make atonement for the whole Israelite community, and they will be forgiven,(AZ) for it was not intentional(BA) and they have presented to the Lord for their wrong a food offering(BB) and a sin offering.(BC) 26 The whole Israelite community and the foreigners residing among them will be forgiven, because all the people were involved in the unintentional wrong.(BD)

27 “‘But if just one person sins unintentionally,(BE) that person must bring a year-old female goat for a sin offering.(BF) 28 The priest is to make atonement(BG) before the Lord for the one who erred by sinning unintentionally, and when atonement has been made, that person will be forgiven.(BH) 29 One and the same law applies to everyone who sins unintentionally, whether a native-born Israelite or a foreigner residing among you.(BI)

30 “‘But anyone who sins defiantly,(BJ) whether native-born or foreigner,(BK) blasphemes the Lord(BL) and must be cut off from the people of Israel.(BM) 31 Because they have despised(BN) the Lord’s word and broken his commands,(BO) they must surely be cut off; their guilt remains on them.(BP)’”

The Sabbath-Breaker Put to Death

32 While the Israelites were in the wilderness,(BQ) a man was found gathering wood on the Sabbath day.(BR) 33 Those who found him gathering wood brought him to Moses and Aaron and the whole assembly, 34 and they kept him in custody, because it was not clear what should be done to him.(BS) 35 Then the Lord said to Moses, “The man must die.(BT) The whole assembly must stone him outside the camp.(BU) 36 So the assembly took him outside the camp and stoned him(BV) to death,(BW) as the Lord commanded Moses.(BX)

Tassels on Garments

37 The Lord said to Moses, 38 “Speak to the Israelites and say to them: ‘Throughout the generations to come(BY) you are to make tassels on the corners of your garments,(BZ) with a blue cord on each tassel. 39 You will have these tassels to look at and so you will remember(CA) all the commands of the Lord, that you may obey them and not prostitute yourselves(CB) by chasing after the lusts of your own hearts(CC) and eyes. 40 Then you will remember to obey all my commands(CD) and will be consecrated to your God.(CE) 41 I am the Lord your God, who brought you out of Egypt to be your God.(CF) I am the Lord your God.(CG)’”

Footnotes

  1. Numbers 15:4 That is, probably about 3 1/2 pounds or about 1.6 kilograms
  2. Numbers 15:4 That is, about 1 quart or about 1 liter; also in verse 5
  3. Numbers 15:6 That is, probably about 7 pounds or about 3.2 kilograms
  4. Numbers 15:6 That is, about 1 1/3 quarts or about 1.3 liters; also in verse 7
  5. Numbers 15:9 That is, probably about 11 pounds or about 5 kilograms
  6. Numbers 15:9 That is, about 2 quarts or about 1.9 liters; also in verse 10
  7. Numbers 15:24 Or purification offering; also in verses 25 and 27