Add parallel Print Page Options

24 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù. Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:

“Ó wí pé Balaamu ọmọ Beori,
    òwe ẹni tí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀,
Òwe ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,
    ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,
    ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì là:

“Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu,
    àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!

“Gẹ́gẹ́ bí Àfonífojì tí ó tàn jáde,
    gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá,
gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn,
    gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
Omi yóò sàn láti inú garawa:
    èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.

“Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ;
    ìjọba wọn yóò di gbígbéga.

“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá;
    wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré.
Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run,
    wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú;
    wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
(A)Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún,
    bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn?

“Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ,
    kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”

10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí. 11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”

12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé, 13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’? 14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”

Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ẹ̀kẹrin Balaamu

15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe:

“Òwe Balaamu ọmọ Beori,
    òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 Ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí,
    tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo,
tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,
    ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:

17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí,
    Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́.
Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu;
    yóò yọ jáde láti Israẹli.
Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu,
    yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 Wọn yóò borí Edomu;
    yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀,
    ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu
    yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”

Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ìkẹyìn Balaamu

20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:

“Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
    ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”

21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:

“Ibùgbé rẹ ní ààbò,
    ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun
    nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”

23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:

“Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24     Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu;
wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi,
    ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”

25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.

24 Now when Balaam saw that it pleased the Lord to bless Israel,(A) he did not resort to divination(B) as at other times, but turned his face toward the wilderness.(C) When Balaam looked out and saw Israel encamped tribe by tribe, the Spirit of God came on him(D) and he spoke his message:

“The prophecy of Balaam son of Beor,
    the prophecy of one whose eye sees clearly,(E)
the prophecy of one who hears the words of God,(F)
    who sees a vision from the Almighty,[a](G)
    who falls prostrate, and whose eyes are opened:

“How beautiful are your tents,(H) Jacob,
    your dwelling places, Israel!

“Like valleys they spread out,
    like gardens beside a river,(I)
like aloes(J) planted by the Lord,
    like cedars beside the waters.(K)
Water will flow from their buckets;
    their seed will have abundant water.

“Their king will be greater than Agag;(L)
    their kingdom will be exalted.(M)

“God brought them out of Egypt;
    they have the strength of a wild ox.
They devour hostile nations
    and break their bones in pieces;(N)
    with their arrows they pierce them.(O)
Like a lion they crouch and lie down,
    like a lioness(P)—who dares to rouse them?

“May those who bless you be blessed(Q)
    and those who curse you be cursed!”(R)

10 Then Balak’s anger burned(S) against Balaam. He struck his hands together(T) and said to him, “I summoned you to curse my enemies,(U) but you have blessed them(V) these three times.(W) 11 Now leave at once and go home!(X) I said I would reward you handsomely,(Y) but the Lord has kept you from being rewarded.”

12 Balaam answered Balak, “Did I not tell the messengers you sent me,(Z) 13 ‘Even if Balak gave me all the silver and gold in his palace, I could not do anything of my own accord, good or bad, to go beyond the command of the Lord(AA)—and I must say only what the Lord says’?(AB) 14 Now I am going back to my people, but come, let me warn you of what this people will do to your people in days to come.”(AC)

Balaam’s Fourth Message

15 Then he spoke his message:

“The prophecy of Balaam son of Beor,
    the prophecy of one whose eye sees clearly,
16 the prophecy of one who hears the words(AD) of God,
    who has knowledge from the Most High,(AE)
who sees a vision from the Almighty,
    who falls prostrate, and whose eyes are opened:

17 “I see him, but not now;
    I behold him, but not near.(AF)
A star will come out of Jacob;(AG)
    a scepter will rise out of Israel.(AH)
He will crush the foreheads of Moab,(AI)
    the skulls[b](AJ) of[c] all the people of Sheth.[d]
18 Edom(AK) will be conquered;
    Seir,(AL) his enemy, will be conquered,(AM)
    but Israel(AN) will grow strong.
19 A ruler will come out of Jacob(AO)
    and destroy the survivors of the city.”

Balaam’s Fifth Message

20 Then Balaam saw Amalek(AP) and spoke his message:

“Amalek was first among the nations,
    but their end will be utter destruction.”(AQ)

Balaam’s Sixth Message

21 Then he saw the Kenites(AR) and spoke his message:

“Your dwelling place is secure,(AS)
    your nest is set in a rock;
22 yet you Kenites will be destroyed
    when Ashur(AT) takes you captive.”

Balaam’s Seventh Message

23 Then he spoke his message:

“Alas! Who can live when God does this?[e]
24     Ships will come from the shores of Cyprus;(AU)
they will subdue Ashur(AV) and Eber,(AW)
    but they too will come to ruin.(AX)

25 Then Balaam(AY) got up and returned home, and Balak went his own way.

Footnotes

  1. Numbers 24:4 Hebrew Shaddai; also in verse 16
  2. Numbers 24:17 Samaritan Pentateuch (see also Jer. 48:45); the meaning of the word in the Masoretic Text is uncertain.
  3. Numbers 24:17 Or possibly Moab, / batter
  4. Numbers 24:17 Or all the noisy boasters
  5. Numbers 24:23 Masoretic Text; with a different word division of the Hebrew The people from the islands will gather from the north.