Add parallel Print Page Options

Àwọn ẹ̀yà Lefi

Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.

(A)Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari. Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà. Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.

(B)(C) Olúwa sọ fún Mose pé, “Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́. Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́. Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́. Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli. 10 Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”

11 (D)Olúwa tún sọ fún Mose pé, 12 “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi, 13 nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”

Kíka àwọn ọmọ Lefi

14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé, 15 (E)“Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè” 16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

17 (F)Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi:

Gerṣoni, Kohati àti Merari.

18 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni:

Libni àti Ṣimei.

19 Àwọn ìdílé Kohati ni:

Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.

20 Àwọn ìdílé Merari ni:

Mahili àti Muṣi.

Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.

21 Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.

22 Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (7,500).

23 Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.

24 Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.

25 Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, 26 aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.

27 Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.

28 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá-mẹ́rin ó-lé-ẹgbẹ̀ta (8,600),

tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.

29 Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.

30 Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.

31 Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.

32 Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.

33 Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.

34 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n (6,200).

35 Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili.

Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.

36 Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn; 37 Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.

38 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé.

Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli.

Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.

39 Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá-mọ́kànlá (22,000).

40 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn. 41 Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”

42 Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un. 43 Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbàá-mọ́kànlá ó lé ọ̀rìnlúgba ó-dínméje (22,273).

44 Olúwa tún sọ fún Mose pé, 45 (G)Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa. 46 Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje (273) àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ, 47 ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún (5) lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera. 48 Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.

49 Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà. 50 Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùn-dínlógójì (1,365) gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli. 51 Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

The Levites

This is the account of the family of Aaron and Moses(A) at the time the Lord spoke to Moses at Mount Sinai.(B)

The names of the sons of Aaron were Nadab the firstborn(C) and Abihu, Eleazar and Ithamar.(D) Those were the names of Aaron’s sons, the anointed priests,(E) who were ordained to serve as priests. Nadab and Abihu, however, died before the Lord(F) when they made an offering with unauthorized fire before him in the Desert of Sinai.(G) They had no sons, so Eleazar and Ithamar(H) served as priests during the lifetime of their father Aaron.(I)

The Lord said to Moses, “Bring the tribe of Levi(J) and present them to Aaron the priest to assist him.(K) They are to perform duties for him and for the whole community(L) at the tent of meeting by doing the work(M) of the tabernacle. They are to take care of all the furnishings of the tent of meeting, fulfilling the obligations of the Israelites by doing the work of the tabernacle. Give the Levites to Aaron and his sons;(N) they are the Israelites who are to be given wholly to him.[a] 10 Appoint Aaron(O) and his sons to serve as priests;(P) anyone else who approaches the sanctuary is to be put to death.”(Q)

11 The Lord also said to Moses, 12 “I have taken the Levites(R) from among the Israelites in place of the first male offspring(S) of every Israelite woman. The Levites are mine,(T) 13 for all the firstborn are mine.(U) When I struck down all the firstborn in Egypt, I set apart for myself every firstborn in Israel, whether human or animal. They are to be mine. I am the Lord.”(V)

14 The Lord said to Moses in the Desert of Sinai,(W) 15 “Count(X) the Levites by their families and clans. Count every male a month old or more.”(Y) 16 So Moses counted them, as he was commanded by the word of the Lord.

17 These were the names of the sons of Levi:(Z)

Gershon,(AA) Kohath(AB) and Merari.(AC)

18 These were the names of the Gershonite clans:

Libni and Shimei.(AD)

19 The Kohathite clans:

Amram, Izhar, Hebron and Uzziel.(AE)

20 The Merarite clans:(AF)

Mahli and Mushi.(AG)

These were the Levite clans, according to their families.

21 To Gershon(AH) belonged the clans of the Libnites and Shimeites;(AI) these were the Gershonite clans. 22 The number of all the males a month old or more who were counted was 7,500. 23 The Gershonite clans were to camp on the west, behind the tabernacle.(AJ) 24 The leader of the families of the Gershonites was Eliasaph son of Lael. 25 At the tent of meeting the Gershonites were responsible for the care of the tabernacle(AK) and tent, its coverings,(AL) the curtain at the entrance(AM) to the tent of meeting,(AN) 26 the curtains of the courtyard(AO), the curtain at the entrance to the courtyard surrounding the tabernacle and altar,(AP) and the ropes(AQ)—and everything(AR) related to their use.

27 To Kohath(AS) belonged the clans of the Amramites, Izharites, Hebronites and Uzzielites;(AT) these were the Kohathite(AU) clans. 28 The number of all the males a month old or more(AV) was 8,600.[b] The Kohathites were responsible(AW) for the care of the sanctuary.(AX) 29 The Kohathite clans were to camp on the south side(AY) of the tabernacle. 30 The leader of the families of the Kohathite clans was Elizaphan(AZ) son of Uzziel. 31 They were responsible for the care of the ark,(BA) the table,(BB) the lampstand,(BC) the altars,(BD) the articles(BE) of the sanctuary used in ministering, the curtain,(BF) and everything related to their use.(BG) 32 The chief leader of the Levites was Eleazar(BH) son of Aaron, the priest. He was appointed over those who were responsible(BI) for the care of the sanctuary.(BJ)

33 To Merari belonged the clans of the Mahlites and the Mushites;(BK) these were the Merarite clans.(BL) 34 The number of all the males a month old or more(BM) who were counted was 6,200. 35 The leader of the families of the Merarite clans was Zuriel son of Abihail; they were to camp on the north side of the tabernacle.(BN) 36 The Merarites were appointed(BO) to take care of the frames of the tabernacle,(BP) its crossbars,(BQ) posts,(BR) bases, all its equipment, and everything related to their use,(BS) 37 as well as the posts of the surrounding courtyard(BT) with their bases, tent pegs(BU) and ropes.

38 Moses and Aaron and his sons were to camp to the east(BV) of the tabernacle, toward the sunrise, in front of the tent of meeting.(BW) They were responsible for the care of the sanctuary(BX) on behalf of the Israelites. Anyone else who approached the sanctuary was to be put to death.(BY)

39 The total number of Levites counted(BZ) at the Lord’s command by Moses and Aaron according to their clans, including every male a month old or more, was 22,000.(CA)

40 The Lord said to Moses, “Count all the firstborn Israelite males who are a month old or more(CB) and make a list of their names.(CC) 41 Take the Levites for me in place of all the firstborn of the Israelites,(CD) and the livestock of the Levites in place of all the firstborn of the livestock of the Israelites. I am the Lord.”(CE)

42 So Moses counted all the firstborn of the Israelites, as the Lord commanded him. 43 The total number of firstborn males a month old or more,(CF) listed by name, was 22,273.(CG)

44 The Lord also said to Moses, 45 “Take the Levites in place of all the firstborn of Israel, and the livestock of the Levites in place of their livestock. The Levites are to be mine.(CH) I am the Lord.(CI) 46 To redeem(CJ) the 273 firstborn Israelites who exceed the number of the Levites, 47 collect five shekels[c](CK) for each one, according to the sanctuary shekel,(CL) which weighs twenty gerahs.(CM) 48 Give the money for the redemption(CN) of the additional Israelites to Aaron and his sons.”(CO)

49 So Moses collected the redemption money(CP) from those who exceeded the number redeemed by the Levites. 50 From the firstborn of the Israelites(CQ) he collected silver weighing 1,365 shekels,[d](CR) according to the sanctuary shekel. 51 Moses gave the redemption money to Aaron and his sons, as he was commanded by the word of the Lord.

Footnotes

  1. Numbers 3:9 Most manuscripts of the Masoretic Text; some manuscripts of the Masoretic Text, Samaritan Pentateuch and Septuagint (see also 8:16) to me
  2. Numbers 3:28 Hebrew; some Septuagint manuscripts 8,300
  3. Numbers 3:47 That is, about 2 ounces or about 58 grams
  4. Numbers 3:50 That is, about 35 pounds or about 16 kilograms