Add parallel Print Page Options

Gbígbẹ̀san lára àwọn ọmọ Midiani

31 Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”

Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn. Rán ẹgbẹ̀rún (1,000) ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún (1,000) ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá-mẹ́fà (12,000) ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun. Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún (1,000) láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.

Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn. Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori. Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn. 10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn. 11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran. 12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.

13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó. 14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹ̀rún (1,000) àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún (1,000) tí wọ́n ti ogun dé.

15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí? 16 (A)Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa. 17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin, 18 Ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.

19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje, Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́. 20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”

21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose. 22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé. 23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi. 24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”

Pínpín ogún

25 Olúwa sọ fún Mose pé, 26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn. 27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ. 28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà: ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran. 29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa. 30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, (50) yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.” 31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n (675,000) ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn. 33 Ẹgbàá-mẹ́rìn-dínlógójì (72,000) màlúù 34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin (61,000) kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, 35 Pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá-mẹ́rìn-dínlógún, (32,000) ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.

36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́:

ẹgbàáméjì-dínláàdọ́san (337,500) ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn. 37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó-dínmẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (675) àgùntàn;

38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàáméjì-dínlógún, (36,000) tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàdọ́rin (72);

39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, (30,500) tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta; (61).

40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàámẹ́jọ (16,000) ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n. (32).

41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.

42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun. 43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá-méjì-dínláàdọ́sàn-án ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (337,500) àgùntàn, 44 pẹ̀lú ẹgbàáméjì-dínlógún (36,000) màlúù 45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàámẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. (30,500) 46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàámẹ́jọ; (16,000). 47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta (50) ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.

48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose. 49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín. 50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”

51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́. 52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá-mẹ́jọ ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta (16,750) ṣékélì. 53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀. 54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.

Vengeance on the Midianites

31 The Lord said to Moses, “Take vengeance on the Midianites(A) for the Israelites. After that, you will be gathered to your people.(B)

So Moses said to the people, “Arm some of your men to go to war against the Midianites so that they may carry out the Lord’s vengeance(C) on them. Send into battle a thousand men from each of the tribes of Israel.” So twelve thousand men armed for battle,(D) a thousand from each tribe, were supplied from the clans of Israel. Moses sent them into battle,(E) a thousand from each tribe, along with Phinehas(F) son of Eleazar, the priest, who took with him articles from the sanctuary(G) and the trumpets(H) for signaling.

They fought against Midian, as the Lord commanded Moses,(I) and killed every man.(J) Among their victims were Evi, Rekem, Zur, Hur and Reba(K)—the five kings of Midian.(L) They also killed Balaam son of Beor(M) with the sword.(N) The Israelites captured the Midianite women(O) and children and took all the Midianite herds, flocks and goods as plunder.(P) 10 They burned(Q) all the towns where the Midianites had settled, as well as all their camps.(R) 11 They took all the plunder and spoils, including the people and animals,(S) 12 and brought the captives, spoils(T) and plunder to Moses and Eleazar the priest and the Israelite assembly(U) at their camp on the plains of Moab, by the Jordan across from Jericho.(V)

13 Moses, Eleazar the priest and all the leaders of the community went to meet them outside the camp. 14 Moses was angry with the officers of the army(W)—the commanders of thousands and commanders of hundreds—who returned from the battle.

15 “Have you allowed all the women to live?” he asked them. 16 “They were the ones who followed Balaam’s advice(X) and enticed the Israelites to be unfaithful to the Lord in the Peor incident,(Y) so that a plague(Z) struck the Lord’s people. 17 Now kill all the boys. And kill every woman who has slept with a man,(AA) 18 but save for yourselves every girl who has never slept with a man.

19 “Anyone who has killed someone or touched someone who was killed(AB) must stay outside the camp seven days.(AC) On the third and seventh days you must purify yourselves(AD) and your captives. 20 Purify every garment(AE) as well as everything made of leather, goat hair or wood.(AF)

21 Then Eleazar the priest said to the soldiers who had gone into battle,(AG) “This is what is required by the law that the Lord gave Moses: 22 Gold, silver, bronze, iron,(AH) tin, lead 23 and anything else that can withstand fire must be put through the fire,(AI) and then it will be clean. But it must also be purified with the water of cleansing.(AJ) And whatever cannot withstand fire must be put through that water. 24 On the seventh day wash your clothes and you will be clean.(AK) Then you may come into the camp.(AL)

Dividing the Spoils

25 The Lord said to Moses, 26 “You and Eleazar the priest and the family heads(AM) of the community are to count all the people(AN) and animals that were captured.(AO) 27 Divide(AP) the spoils equally between the soldiers who took part in the battle and the rest of the community. 28 From the soldiers who fought in the battle, set apart as tribute for the Lord(AQ) one out of every five hundred, whether people, cattle, donkeys or sheep. 29 Take this tribute from their half share and give it to Eleazar the priest as the Lord’s part. 30 From the Israelites’ half, select one out of every fifty, whether people, cattle, donkeys, sheep or other animals. Give them to the Levites, who are responsible for the care of the Lord’s tabernacle.(AR) 31 So Moses and Eleazar the priest did as the Lord commanded Moses.

32 The plunder remaining from the spoils(AS) that the soldiers took was 675,000 sheep, 33 72,000 cattle, 34 61,000 donkeys 35 and 32,000 women who had never slept with a man.

36 The half share of those who fought in the battle was:

337,500 sheep, 37 of which the tribute for the Lord(AT) was 675;

38 36,000 cattle, of which the tribute for the Lord was 72;

39 30,500 donkeys, of which the tribute for the Lord was 61;

40 16,000 people, of whom the tribute for the Lord was 32.

41 Moses gave the tribute to Eleazar the priest as the Lord’s part,(AU) as the Lord commanded Moses.(AV)

42 The half belonging to the Israelites, which Moses set apart from that of the fighting men— 43 the community’s half—was 337,500 sheep, 44 36,000 cattle, 45 30,500 donkeys 46 and 16,000 people. 47 From the Israelites’ half, Moses selected one out of every fifty people and animals, as the Lord commanded him, and gave them to the Levites, who were responsible for the care of the Lord’s tabernacle.

48 Then the officers(AW) who were over the units of the army—the commanders of thousands and commanders of hundreds—went to Moses 49 and said to him, “Your servants have counted(AX) the soldiers under our command, and not one is missing.(AY) 50 So we have brought as an offering to the Lord the gold articles each of us acquired—armlets, bracelets, signet rings, earrings and necklaces—to make atonement for ourselves(AZ) before the Lord.”

51 Moses and Eleazar the priest accepted from them the gold—all the crafted articles. 52 All the gold from the commanders of thousands and commanders of hundreds that Moses and Eleazar presented as a gift to the Lord weighed 16,750 shekels.[a] 53 Each soldier had taken plunder(BA) for himself. 54 Moses and Eleazar the priest accepted the gold from the commanders of thousands and commanders of hundreds and brought it into the tent of meeting(BB) as a memorial(BC) for the Israelites before the Lord.

Footnotes

  1. Numbers 31:52 That is, about 420 pounds or about 190 kilograms