Orin Solomoni 5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Olólùfẹ́
5 Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
mo ti kó òjìá pẹ̀lú òórùn dídùn mi jọ.
Mo ti jẹ afárá mi pẹ̀lú oyin mi;
mo ti mu ọtí wáìnì mi pẹ̀lú wàrà mi.
Ọ̀rẹ́
Ẹ jẹ, ẹ̀yin ọ̀rẹ́, ẹ mu,
àní ẹ mu àmuyó, ẹ̀yin olùfẹ́.
Olùfẹ́
2 Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.
“Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,
àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi
Orí mi kún fún omi ìrì,
irun mi kún fún òtútù òru.”
3 Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?
Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi
ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?
4 Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
inú mi sì yọ́ sí i
5 Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,
òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn
sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn
6 Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ
ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.
Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.
Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn
7 Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.
Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;
wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.
Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!
8 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,
kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?
Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.
Ọ̀rẹ́
9 Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ
tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?
Olùfẹ́
10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ.
11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ
ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò
12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,
tí a fi wàrà wẹ̀,
tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
tí ó sun òórùn tùràrí dídùn
Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì
ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn
14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká
Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán
tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mábù
tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára
Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,
tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.
16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀
ó wu ni pátápátá.
Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.
Song of Songs 5
New International Version
He
5 I have come into my garden,(A) my sister, my bride;(B)
I have gathered my myrrh with my spice.
I have eaten my honeycomb and my honey;
I have drunk my wine and my milk.(C)
Friends
Eat, friends, and drink;
drink your fill of love.
She
2 I slept but my heart was awake.
Listen! My beloved is knocking:
“Open to me, my sister, my darling,
my dove,(D) my flawless(E) one.(F)
My head is drenched with dew,
my hair with the dampness of the night.”
3 I have taken off my robe—
must I put it on again?
I have washed my feet—
must I soil them again?
4 My beloved thrust his hand through the latch-opening;
my heart began to pound for him.
5 I arose to open for my beloved,
and my hands dripped with myrrh,(G)
my fingers with flowing myrrh,
on the handles of the bolt.
6 I opened for my beloved,(H)
but my beloved had left; he was gone.(I)
My heart sank at his departure.[a]
I looked(J) for him but did not find him.
I called him but he did not answer.
7 The watchmen found me
as they made their rounds in the city.(K)
They beat me, they bruised me;
they took away my cloak,
those watchmen of the walls!
8 Daughters of Jerusalem, I charge you(L)—
if you find my beloved,(M)
what will you tell him?
Tell him I am faint with love.(N)
Friends
9 How is your beloved better than others,
most beautiful of women?(O)
How is your beloved better than others,
that you so charge us?
She
10 My beloved is radiant and ruddy,
outstanding among ten thousand.(P)
11 His head is purest gold;
his hair is wavy
and black as a raven.
12 His eyes are like doves(Q)
by the water streams,
washed in milk,(R)
mounted like jewels.
13 His cheeks(S) are like beds of spice(T)
yielding perfume.
His lips are like lilies(U)
dripping with myrrh.(V)
14 His arms are rods of gold
set with topaz.
His body is like polished ivory
decorated with lapis lazuli.(W)
15 His legs are pillars of marble
set on bases of pure gold.
His appearance is like Lebanon,(X)
choice as its cedars.
16 His mouth(Y) is sweetness itself;
he is altogether lovely.
This is my beloved,(Z) this is my friend,
daughters of Jerusalem.(AA)
Footnotes
- Song of Songs 5:6 Or heart had gone out to him when he spoke
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.