Add parallel Print Page Options

Olólùfẹ́

Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
    mo ti kó òjìá pẹ̀lú òórùn dídùn mi jọ.
Mo ti jẹ afárá mi pẹ̀lú oyin mi;
    mo ti mu ọtí wáìnì mi pẹ̀lú wàrà mi.

Ọ̀rẹ́

Ẹ jẹ, ẹ̀yin ọ̀rẹ́, ẹ mu,
    àní ẹ mu àmuyó, ẹ̀yin olùfẹ́.

Olùfẹ́

Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
    Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.
“Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,
    àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi
Orí mi kún fún omi ìrì,
    irun mi kún fún òtútù òru.”
Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?
Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?
Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
    inú mi sì yọ́ sí i
Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,
òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn
    sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn
Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ
    ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.
Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.
    Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn
Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
    bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.
Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;
    wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.
    Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
    bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,
kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?
    Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.

Ọ̀rẹ́

Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
    ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ
    tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?

Olùfẹ́

10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
    ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ.
11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
    ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ
    ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò
12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
    ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,
tí a fi wàrà wẹ̀,
    tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
    tí ó sun òórùn tùràrí dídùn
Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì
    ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn
14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
    tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká
Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán
    tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mábù
    tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára
Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,
    tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.
16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀
    ó wu ni pátápátá.
Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
    Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.