Add parallel Print Page Options

106 (A)Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún
    Olúwa, nítorí tí ó ṣeun.

Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
    Nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa,
    ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?
    Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.

Rántí mi, Olúwa,
    Nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn,
    wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn,
    kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn,
    ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.

Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe,
    àwa ti ṣe ohun tí kò dá a,
    a sì ti hùwà búburú
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti,
    iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn,
wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ,
    gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun pupa
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ
    láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀
O bá Òkun pupa wí, ó sì gbẹ;
    o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn
    láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn, bẹ́ẹ̀ ni
    kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́
    wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.

13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe
    wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́
    nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún
    ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.

16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose
    pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì
    ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀;
    iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù
    wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà
    sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n
    ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu
    àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun pupa
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run
    bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn,
tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà
    tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.

24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà
    wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn
    wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
    kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè
    láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori,
    wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà
29 Wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe
    àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i,
    àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti
    fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú,
    ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ẹ̀mí Ọlọ́run.
    Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.

34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run
    gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sọ fún wọn,
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
    wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn
    tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ
    àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
    Ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn
ọmọbìnrin wọn.
    Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́,
    wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.

40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀
    ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,
    àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú
    wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,
    Síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i
    wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro
    nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;
45 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn
    Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn
    ó mú wọn rí àánú.

47 (B)Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa,
    kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí,
láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ
    láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.

48 Olùbùkún ni Olúwa,
    Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran.

Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!”

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

Psalm 106(A)

Praise the Lord.[a](B)

Give thanks to the Lord, for he is good;(C)
    his love endures forever.(D)

Who can proclaim the mighty acts(E) of the Lord
    or fully declare his praise?
Blessed are those who act justly,(F)
    who always do what is right.(G)

Remember me,(H) Lord, when you show favor(I) to your people,
    come to my aid(J) when you save them,
that I may enjoy the prosperity(K) of your chosen ones,(L)
    that I may share in the joy(M) of your nation
    and join your inheritance(N) in giving praise.

We have sinned,(O) even as our ancestors(P) did;
    we have done wrong and acted wickedly.(Q)
When our ancestors were in Egypt,
    they gave no thought(R) to your miracles;
they did not remember(S) your many kindnesses,
    and they rebelled by the sea,(T) the Red Sea.[b]
Yet he saved them(U) for his name’s sake,(V)
    to make his mighty power(W) known.
He rebuked(X) the Red Sea, and it dried up;(Y)
    he led them through(Z) the depths as through a desert.
10 He saved them(AA) from the hand of the foe;(AB)
    from the hand of the enemy he redeemed them.(AC)
11 The waters covered(AD) their adversaries;
    not one of them survived.
12 Then they believed his promises
    and sang his praise.(AE)

13 But they soon forgot(AF) what he had done
    and did not wait for his plan to unfold.(AG)
14 In the desert(AH) they gave in to their craving;
    in the wilderness(AI) they put God to the test.(AJ)
15 So he gave them(AK) what they asked for,
    but sent a wasting disease(AL) among them.

16 In the camp they grew envious(AM) of Moses
    and of Aaron, who was consecrated to the Lord.
17 The earth opened(AN) up and swallowed Dathan;(AO)
    it buried the company of Abiram.(AP)
18 Fire blazed(AQ) among their followers;
    a flame consumed the wicked.
19 At Horeb they made a calf(AR)
    and worshiped an idol cast from metal.
20 They exchanged their glorious God(AS)
    for an image of a bull, which eats grass.
21 They forgot the God(AT) who saved them,
    who had done great things(AU) in Egypt,
22 miracles in the land of Ham(AV)
    and awesome deeds(AW) by the Red Sea.
23 So he said he would destroy(AX) them—
    had not Moses, his chosen one,
stood in the breach(AY) before him
    to keep his wrath from destroying them.

24 Then they despised(AZ) the pleasant land;(BA)
    they did not believe(BB) his promise.
25 They grumbled(BC) in their tents
    and did not obey the Lord.
26 So he swore(BD) to them with uplifted hand
    that he would make them fall in the wilderness,(BE)
27 make their descendants fall among the nations
    and scatter(BF) them throughout the lands.

28 They yoked themselves to the Baal of Peor(BG)
    and ate sacrifices offered to lifeless gods;
29 they aroused the Lord’s anger(BH) by their wicked deeds,(BI)
    and a plague(BJ) broke out among them.
30 But Phinehas(BK) stood up and intervened,
    and the plague was checked.(BL)
31 This was credited to him(BM) as righteousness
    for endless generations(BN) to come.
32 By the waters of Meribah(BO) they angered the Lord,
    and trouble came to Moses because of them;
33 for they rebelled(BP) against the Spirit(BQ) of God,
    and rash words came from Moses’ lips.[c](BR)

34 They did not destroy(BS) the peoples
    as the Lord had commanded(BT) them,
35 but they mingled(BU) with the nations
    and adopted their customs.
36 They worshiped their idols,(BV)
    which became a snare(BW) to them.
37 They sacrificed their sons(BX)
    and their daughters to false gods.(BY)
38 They shed innocent blood,
    the blood of their sons(BZ) and daughters,
whom they sacrificed to the idols of Canaan,
    and the land was desecrated by their blood.
39 They defiled themselves(CA) by what they did;
    by their deeds they prostituted(CB) themselves.

40 Therefore the Lord was angry(CC) with his people
    and abhorred his inheritance.(CD)
41 He gave them into the hands(CE) of the nations,
    and their foes ruled over them.
42 Their enemies oppressed(CF) them
    and subjected them to their power.
43 Many times he delivered them,(CG)
    but they were bent on rebellion(CH)
    and they wasted away in their sin.
44 Yet he took note of their distress
    when he heard their cry;(CI)
45 for their sake he remembered his covenant(CJ)
    and out of his great love(CK) he relented.(CL)
46 He caused all who held them captive
    to show them mercy.(CM)

47 Save us,(CN) Lord our God,
    and gather us(CO) from the nations,
that we may give thanks(CP) to your holy name(CQ)
    and glory in your praise.

48 Praise be to the Lord, the God of Israel,
    from everlasting to everlasting.

Let all the people say, “Amen!”(CR)

Praise the Lord.

Footnotes

  1. Psalm 106:1 Hebrew Hallelu Yah; also in verse 48
  2. Psalm 106:7 Or the Sea of Reeds; also in verses 9 and 22
  3. Psalm 106:33 Or against his spirit, / and rash words came from his lips