Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.

109 Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún
    Má ṣe dákẹ́
Nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn
    ti ya ẹnu wọn sí mi
    wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi
Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri;
    wọ́n bá mi jà láìnídìí
Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi,
    ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi
    àti ìríra fún ìfẹ́ mi.

Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ
    jẹ́ kí àwọn olùfisùn
    dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́
    kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀
(A)Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú
    kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀
Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba
    kí aya rẹ̀ sì di opó
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri
    kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní
    jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un
    tàbí kí wọn káàánú lórí
    àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò
    kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí
    ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa
    Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa
    kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.

16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú,
    ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú,
    kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀:
    bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù
    bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní
    ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá;
    àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.

21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè,
    ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ
    Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí,
    àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́,
    mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà
    ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
25 (B)Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi;
    nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.

26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi;
    gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí
    wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre;
    Nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n,
    ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú
    kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.

30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi
    ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní
    láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.

Psalm 109

For the director of music. Of David. A psalm.

My God, whom I praise,(A)
    do not remain silent,(B)
for people who are wicked and deceitful(C)
    have opened their mouths against me;
    they have spoken against me with lying tongues.(D)
With words of hatred(E) they surround me;
    they attack me without cause.(F)
In return for my friendship they accuse me,
    but I am a man of prayer.(G)
They repay me evil for good,(H)
    and hatred for my friendship.

Appoint someone evil to oppose my enemy;
    let an accuser(I) stand at his right hand.
When he is tried, let him be found guilty,(J)
    and may his prayers condemn(K) him.
May his days be few;(L)
    may another take his place(M) of leadership.
May his children be fatherless
    and his wife a widow.(N)
10 May his children be wandering beggars;(O)
    may they be driven[a] from their ruined homes.
11 May a creditor(P) seize all he has;
    may strangers plunder(Q) the fruits of his labor.(R)
12 May no one extend kindness to him
    or take pity(S) on his fatherless children.
13 May his descendants be cut off,(T)
    their names blotted out(U) from the next generation.
14 May the iniquity of his fathers(V) be remembered before the Lord;
    may the sin of his mother never be blotted out.
15 May their sins always remain before(W) the Lord,
    that he may blot out their name(X) from the earth.

16 For he never thought of doing a kindness,
    but hounded to death the poor
    and the needy(Y) and the brokenhearted.(Z)
17 He loved to pronounce a curse—
    may it come back on him.(AA)
He found no pleasure in blessing—
    may it be far from him.
18 He wore cursing(AB) as his garment;
    it entered into his body like water,(AC)
    into his bones like oil.
19 May it be like a cloak wrapped(AD) about him,
    like a belt tied forever around him.
20 May this be the Lord’s payment(AE) to my accusers,
    to those who speak evil(AF) of me.

21 But you, Sovereign Lord,
    help me for your name’s sake;(AG)
    out of the goodness of your love,(AH) deliver me.(AI)
22 For I am poor and needy,
    and my heart is wounded within me.
23 I fade away like an evening shadow;(AJ)
    I am shaken off like a locust.
24 My knees give(AK) way from fasting;(AL)
    my body is thin and gaunt.(AM)
25 I am an object of scorn(AN) to my accusers;
    when they see me, they shake their heads.(AO)

26 Help me,(AP) Lord my God;
    save me according to your unfailing love.
27 Let them know(AQ) that it is your hand,
    that you, Lord, have done it.
28 While they curse,(AR) may you bless;
    may those who attack me be put to shame,
    but may your servant rejoice.(AS)
29 May my accusers be clothed with disgrace
    and wrapped in shame(AT) as in a cloak.

30 With my mouth I will greatly extol the Lord;
    in the great throng(AU) of worshipers I will praise him.
31 For he stands at the right hand(AV) of the needy,
    to save their lives from those who would condemn them.

Footnotes

  1. Psalm 109:10 Septuagint; Hebrew sought