Add parallel Print Page Options

Ti Dafidi.

27 Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi;
    ta ni èmi yóò bẹ̀rù?
Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi,
    ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?

Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi
    láti jẹ ẹran-ara mi,
àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi,
    wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi,
    ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù;
bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,
    nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.

Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa,
    òhun ni èmi yóò máa wá kiri:
kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa
    ní ọjọ́ ayé mi gbogbo,
kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa,
    kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú
    òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀;
níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́;
    yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.

Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè
    ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká;
èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀;
    èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.

Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Háà! Olúwa,
    ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn;
“Wá,” ọkàn mi wí pé, “wá ojú u rẹ̀.”
    Ojú rẹ, Olúwa, ni èmí ń wá.
Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi,
    má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì;
    ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi,
Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí,
    háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀,
    Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa,
    kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú
    nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́,
    nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi,
    wọ́n sì mí ìmí ìkà.

13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé,
    èmi yóò rí ìre Olúwa
    ní ilẹ̀ alààyè.
14 Dúró de Olúwa;
    kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le
    àní dúró de Olúwa.

Psalm 27

Of David.

The Lord is my light(A) and my salvation(B)
    whom shall I fear?
The Lord is the stronghold(C) of my life—
    of whom shall I be afraid?(D)

When the wicked advance against me
    to devour[a] me,
it is my enemies and my foes
    who will stumble and fall.(E)
Though an army besiege me,
    my heart will not fear;(F)
though war break out against me,
    even then I will be confident.(G)

One thing(H) I ask from the Lord,
    this only do I seek:
that I may dwell in the house of the Lord
    all the days of my life,(I)
to gaze on the beauty of the Lord
    and to seek him in his temple.
For in the day of trouble(J)
    he will keep me safe(K) in his dwelling;
he will hide me(L) in the shelter of his sacred tent
    and set me high upon a rock.(M)

Then my head will be exalted(N)
    above the enemies who surround me;(O)
at his sacred tent I will sacrifice(P) with shouts of joy;(Q)
    I will sing(R) and make music(S) to the Lord.

Hear my voice(T) when I call, Lord;
    be merciful to me and answer me.(U)
My heart says of you, “Seek his face!(V)
    Your face, Lord, I will seek.
Do not hide your face(W) from me,
    do not turn your servant away in anger;(X)
    you have been my helper.(Y)
Do not reject me or forsake(Z) me,
    God my Savior.(AA)
10 Though my father and mother forsake me,
    the Lord will receive me.
11 Teach me your way,(AB) Lord;
    lead me in a straight path(AC)
    because of my oppressors.(AD)
12 Do not turn me over to the desire of my foes,
    for false witnesses(AE) rise up against me,
    spouting malicious accusations.

13 I remain confident of this:
    I will see the goodness of the Lord(AF)
    in the land of the living.(AG)
14 Wait(AH) for the Lord;
    be strong(AI) and take heart
    and wait for the Lord.

Footnotes

  1. Psalm 27:2 Or slander