Add parallel Print Page Options

Ti Dafidi.

37 Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,
    kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,
    wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.

Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere;
    torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Ṣe inú dídùn sí Olúwa;
    òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;
    gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,
    àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa,
    kí o sì fi sùúrù dúró dè é;
má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,
    nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.

Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,
    má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,
    ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;
    nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
    wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,
    wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,
    nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.

14 Ènìyàn búburú fa idà yọ,
    wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,
láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,
    láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,
    àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,
    sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,
    ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,
    àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,
    àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.
    Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù;
    wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,
    ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
22 Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
    àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,
    o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
24 Bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,
    nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.

25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;
    síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,
    tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;
    a sì máa bùsi i fún ni.

27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;
    nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,
    kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.

Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,
    ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
    yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,
    ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;
    àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,
    Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,
    nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

34 Dúró de Olúwa,
    kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.
Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;
    nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,
    ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;
    bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;
    nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;
    ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.

39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;
    òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;
    yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,
    nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

Psalm 37[a]

Of David.

Do not fret because of those who are evil
    or be envious(A) of those who do wrong;(B)
for like the grass they will soon wither,(C)
    like green plants they will soon die away.(D)

Trust in the Lord and do good;
    dwell in the land(E) and enjoy safe pasture.(F)
Take delight(G) in the Lord,
    and he will give you the desires of your heart.(H)

Commit your way to the Lord;
    trust in him(I) and he will do this:
He will make your righteous reward(J) shine like the dawn,(K)
    your vindication like the noonday sun.

Be still(L) before the Lord
    and wait patiently(M) for him;
do not fret(N) when people succeed in their ways,(O)
    when they carry out their wicked schemes.(P)

Refrain from anger(Q) and turn from wrath;
    do not fret(R)—it leads only to evil.
For those who are evil will be destroyed,(S)
    but those who hope(T) in the Lord will inherit the land.(U)

10 A little while, and the wicked will be no more;(V)
    though you look for them, they will not be found.
11 But the meek will inherit the land(W)
    and enjoy peace and prosperity.(X)

12 The wicked plot(Y) against the righteous
    and gnash their teeth(Z) at them;
13 but the Lord laughs at the wicked,
    for he knows their day is coming.(AA)

14 The wicked draw the sword(AB)
    and bend the bow(AC)
to bring down the poor and needy,(AD)
    to slay those whose ways are upright.
15 But their swords will pierce their own hearts,(AE)
    and their bows will be broken.(AF)

16 Better the little that the righteous have
    than the wealth(AG) of many wicked;
17 for the power of the wicked will be broken,(AH)
    but the Lord upholds(AI) the righteous.

18 The blameless spend their days under the Lord’s care,(AJ)
    and their inheritance will endure forever.(AK)
19 In times of disaster they will not wither;
    in days of famine they will enjoy plenty.

20 But the wicked will perish:(AL)
    Though the Lord’s enemies are like the flowers of the field,
    they will be consumed, they will go up in smoke.(AM)

21 The wicked borrow and do not repay,
    but the righteous give generously;(AN)
22 those the Lord blesses will inherit the land,
    but those he curses(AO) will be destroyed.(AP)

23 The Lord makes firm the steps(AQ)
    of the one who delights(AR) in him;
24 though he may stumble, he will not fall,(AS)
    for the Lord upholds(AT) him with his hand.

25 I was young and now I am old,
    yet I have never seen the righteous forsaken(AU)
    or their children begging(AV) bread.
26 They are always generous and lend freely;(AW)
    their children will be a blessing.[b](AX)

27 Turn from evil and do good;(AY)
    then you will dwell in the land forever.(AZ)
28 For the Lord loves the just
    and will not forsake his faithful ones.(BA)

Wrongdoers will be completely destroyed[c];
    the offspring of the wicked will perish.(BB)
29 The righteous will inherit the land(BC)
    and dwell in it forever.(BD)

30 The mouths of the righteous utter wisdom,(BE)
    and their tongues speak what is just.
31 The law of their God is in their hearts;(BF)
    their feet do not slip.(BG)

32 The wicked lie in wait(BH) for the righteous,(BI)
    intent on putting them to death;
33 but the Lord will not leave them in the power of the wicked
    or let them be condemned(BJ) when brought to trial.(BK)

34 Hope in the Lord(BL)
    and keep his way.(BM)
He will exalt you to inherit the land;
    when the wicked are destroyed,(BN) you will see(BO) it.

35 I have seen a wicked and ruthless man
    flourishing(BP) like a luxuriant native tree,
36 but he soon passed away and was no more;
    though I looked for him, he could not be found.(BQ)

37 Consider the blameless,(BR) observe the upright;(BS)
    a future awaits those who seek peace.[d](BT)
38 But all sinners(BU) will be destroyed;(BV)
    there will be no future[e] for the wicked.(BW)

39 The salvation(BX) of the righteous comes from the Lord;
    he is their stronghold in time of trouble.(BY)
40 The Lord helps(BZ) them and delivers(CA) them;
    he delivers them from the wicked and saves(CB) them,
    because they take refuge(CC) in him.

Footnotes

  1. Psalm 37:1 This psalm is an acrostic poem, the stanzas of which begin with the successive letters of the Hebrew alphabet.
  2. Psalm 37:26 Or freely; / the names of their children will be used in blessings (see Gen. 48:20); or freely; / others will see that their children are blessed
  3. Psalm 37:28 See Septuagint; Hebrew They will be protected forever
  4. Psalm 37:37 Or upright; / those who seek peace will have posterity
  5. Psalm 37:38 Or posterity