Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Saamu Dafidi.

41 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní:
    Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́:
    yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀
kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀
    yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.

Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi;
    wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé
    “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí,
    wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀;
nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.

Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi;
    èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin
    àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí,
kì yóò dìde mọ́.”
(A)Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé,
    ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi,
tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.

10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi;
    gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi,
    nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
12 Bí ó ṣe tèmi ni
    ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi
ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.

13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli
    láé àti láéláé.
Àmín àti Àmín.

Psalm 41[a]

For the director of music. A psalm of David.

Blessed(A) are those who have regard for the weak;(B)
    the Lord delivers them in times of trouble.(C)
The Lord protects(D) and preserves them—(E)
    they are counted among the blessed in the land—(F)
    he does not give them over to the desire of their foes.(G)
The Lord sustains them on their sickbed(H)
    and restores them from their bed of illness.(I)

I said, “Have mercy(J) on me, Lord;
    heal(K) me, for I have sinned(L) against you.”
My enemies say of me in malice,
    “When will he die and his name perish?(M)
When one of them comes to see me,
    he speaks falsely,(N) while his heart gathers slander;(O)
    then he goes out and spreads(P) it around.

All my enemies whisper together(Q) against me;
    they imagine the worst for me, saying,
“A vile disease has afflicted him;
    he will never get up(R) from the place where he lies.”
Even my close friend,(S)
    someone I trusted,
one who shared my bread,
    has turned[b] against me.(T)

10 But may you have mercy(U) on me, Lord;
    raise me up,(V) that I may repay(W) them.
11 I know that you are pleased with me,(X)
    for my enemy does not triumph over me.(Y)
12 Because of my integrity(Z) you uphold me(AA)
    and set me in your presence forever.(AB)

13 Praise(AC) be to the Lord, the God of Israel,(AD)
    from everlasting to everlasting.
Amen and Amen.(AE)

Footnotes

  1. Psalm 41:1 In Hebrew texts 41:1-13 is numbered 41:2-14.
  2. Psalm 41:9 Hebrew has lifted up his heel