Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi.

Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa,
    kíyèsi àròyé mi.
Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,
    ọba mi àti Ọlọ́run mi,
    nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.

Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi;
    ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀
    èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú;
    bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
Àwọn agbéraga kò le è dúró
    níwájú rẹ̀.
Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
    ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run.
Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn
    ni Olúwa yóò kórìíra.
Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀,
    èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀;
ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba
    sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.

Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ,
    nítorí àwọn ọ̀tá mi,
    mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
(A)Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;
    ọkàn wọn kún fún ìparun.
Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀;
    pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!
    Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.
Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
    nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;
    jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.
Tan ààbò rẹ sórí wọn,
    àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.

12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo;
    ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.

Psalm 5[a]

For the director of music. For pipes. A psalm of David.

Listen(A) to my words, Lord,
    consider my lament.(B)
Hear my cry for help,(C)
    my King and my God,(D)
    for to you I pray.

In the morning,(E) Lord, you hear my voice;
    in the morning I lay my requests before you
    and wait expectantly.(F)
For you are not a God who is pleased with wickedness;
    with you, evil people(G) are not welcome.
The arrogant(H) cannot stand(I)
    in your presence.
You hate(J) all who do wrong;
    you destroy those who tell lies.(K)
The bloodthirsty and deceitful
    you, Lord, detest.
But I, by your great love,
    can come into your house;
in reverence(L) I bow down(M)
    toward your holy temple.(N)

Lead me, Lord, in your righteousness(O)
    because of my enemies—
    make your way straight(P) before me.
Not a word from their mouth can be trusted;
    their heart is filled with malice.
Their throat is an open grave;(Q)
    with their tongues they tell lies.(R)
10 Declare them guilty, O God!
    Let their intrigues be their downfall.
Banish them for their many sins,(S)
    for they have rebelled(T) against you.
11 But let all who take refuge in you be glad;
    let them ever sing for joy.(U)
Spread your protection over them,
    that those who love your name(V) may rejoice in you.(W)

12 Surely, Lord, you bless the righteous;(X)
    you surround them(Y) with your favor as with a shield.(Z)

Footnotes

  1. Psalm 5:1 In Hebrew texts 5:1-12 is numbered 5:2-13.