Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin.

68 Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká;
    kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ,
    kí ó fẹ́ wọn lọ;
bí ìda ti í yọ́ níwájú iná,
    kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn
    kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run;
    kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.

Ẹ kọrin sí Ọlọ́run,
    ẹ kọrin ìyìn sí i,
ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù.
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé
    rẹ̀ mímọ́
Ọlọ́run gbé aláìlera
    kalẹ̀ nínú ìdílé,
ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin,
    ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.

Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run,
    tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, Sela.
Ilẹ̀ mì títí,
    àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde,
níwájú Ọlọ́run,
    ẹni Sinai,
níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run;
    ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀
    nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.

11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀,
    púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ;
    Obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran,
    nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà,
    àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà,
    ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.

15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run;
    òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara,
    ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba
    níbi tí Ọlọ́run fúnrarẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run
    ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún;
    Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga
    ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ;
    ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn:
nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú,
    Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.

19 Olùbùkún ni Olúwa,
    Ọlọ́run Olùgbàlà wa,
ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. Sela.
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà
    àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.

21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
    àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani;
    èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
23 Kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ,
    àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”

24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run,
    ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
25 Àwọn akọrin ní iwájú,
    tí wọn ń lu ṣaworo
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́;
    àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn,
    níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda,
    níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.

28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run;
    fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu
    àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí,
    tí ń gbé láàrín eèsún
ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù
    pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù
títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà:
    tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti;
    Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.

32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé,
    kọrin ìyìn sí Olúwa, Sela.
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè,
    tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
34 Kéde agbára Ọlọ́run,
    ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli,
    tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ;
    Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ.

Olùbùkún ní Ọlọ́run!

Psalm 68[a]

For the director of music. Of David. A psalm. A song.

May God arise,(A) may his enemies be scattered;(B)
    may his foes flee(C) before him.
May you blow them away like smoke—(D)
    as wax melts(E) before the fire,
    may the wicked perish(F) before God.
But may the righteous be glad
    and rejoice(G) before God;
    may they be happy and joyful.

Sing to God, sing in praise of his name,(H)
    extol him who rides on the clouds[b](I);
    rejoice before him—his name is the Lord.(J)
A father to the fatherless,(K) a defender of widows,(L)
    is God in his holy dwelling.(M)
God sets the lonely(N) in families,[c](O)
    he leads out the prisoners(P) with singing;
    but the rebellious live in a sun-scorched land.(Q)

When you, God, went out(R) before your people,
    when you marched through the wilderness,[d](S)
the earth shook,(T) the heavens poured down rain,(U)
    before God, the One of Sinai,(V)
    before God, the God of Israel.(W)
You gave abundant showers,(X) O God;
    you refreshed your weary inheritance.
10 Your people settled in it,
    and from your bounty,(Y) God, you provided(Z) for the poor.

11 The Lord announces the word,
    and the women who proclaim it are a mighty throng:(AA)
12 “Kings and armies flee(AB) in haste;
    the women at home divide the plunder.(AC)
13 Even while you sleep among the sheep pens,[e](AD)
    the wings of my dove are sheathed with silver,
    its feathers with shining gold.”
14 When the Almighty[f] scattered(AE) the kings in the land,
    it was like snow fallen on Mount Zalmon.(AF)

15 Mount Bashan,(AG) majestic mountain,(AH)
    Mount Bashan, rugged mountain,
16 why gaze in envy, you rugged mountain,
    at the mountain where God chooses(AI) to reign,
    where the Lord himself will dwell forever?(AJ)
17 The chariots(AK) of God are tens of thousands
    and thousands of thousands;(AL)
    the Lord has come from Sinai into his sanctuary.[g]
18 When you ascended(AM) on high,(AN)
    you took many captives;(AO)
    you received gifts from people,(AP)
even from[h] the rebellious(AQ)
    that you,[i] Lord God, might dwell there.

19 Praise be to the Lord, to God our Savior,(AR)
    who daily bears our burdens.(AS)
20 Our God is a God who saves;(AT)
    from the Sovereign Lord comes escape from death.(AU)
21 Surely God will crush the heads(AV) of his enemies,
    the hairy crowns of those who go on in their sins.
22 The Lord says, “I will bring them from Bashan;
    I will bring them from the depths of the sea,(AW)
23 that your feet may wade in the blood of your foes,(AX)
    while the tongues of your dogs(AY) have their share.”

24 Your procession, God, has come into view,
    the procession of my God and King into the sanctuary.(AZ)
25 In front are the singers,(BA) after them the musicians;(BB)
    with them are the young women playing the timbrels.(BC)
26 Praise God in the great congregation;(BD)
    praise the Lord in the assembly of Israel.(BE)
27 There is the little tribe(BF) of Benjamin,(BG) leading them,
    there the great throng of Judah’s princes,
    and there the princes of Zebulun and of Naphtali.(BH)

28 Summon your power,(BI) God[j];
    show us your strength,(BJ) our God, as you have done(BK) before.
29 Because of your temple at Jerusalem
    kings will bring you gifts.(BL)
30 Rebuke the beast(BM) among the reeds,(BN)
    the herd of bulls(BO) among the calves of the nations.
Humbled, may the beast bring bars of silver.
    Scatter the nations(BP) who delight in war.(BQ)
31 Envoys will come from Egypt;(BR)
    Cush[k](BS) will submit herself to God.

32 Sing to God, you kingdoms of the earth,(BT)
    sing praise(BU) to the Lord,
33 to him who rides(BV) across the highest heavens, the ancient heavens,
    who thunders(BW) with mighty voice.(BX)
34 Proclaim the power(BY) of God,
    whose majesty(BZ) is over Israel,
    whose power is in the heavens.
35 You, God, are awesome(CA) in your sanctuary;(CB)
    the God of Israel gives power and strength(CC) to his people.(CD)

Praise be to God!(CE)

Footnotes

  1. Psalm 68:1 In Hebrew texts 68:1-35 is numbered 68:2-36.
  2. Psalm 68:4 Or name, / prepare the way for him who rides through the deserts
  3. Psalm 68:6 Or the desolate in a homeland
  4. Psalm 68:7 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verses 19 and 32.
  5. Psalm 68:13 Or the campfires; or the saddlebags
  6. Psalm 68:14 Hebrew Shaddai
  7. Psalm 68:17 Probable reading of the original Hebrew text; Masoretic Text Lord is among them at Sinai in holiness
  8. Psalm 68:18 Or gifts for people, / even
  9. Psalm 68:18 Or they
  10. Psalm 68:28 Many Hebrew manuscripts, Septuagint and Syriac; most Hebrew manuscripts Your God has summoned power for you
  11. Psalm 68:31 That is, the upper Nile region