Add parallel Print Page Options

Adúra ti Dafidi.

86 Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn,
    nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ:
    ìwọ ni Ọlọ́run mi,
gbà ìránṣẹ́ rẹ là
    tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Ṣàánú fún mi, Olúwa,
    nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ,
    nítorí ìwọ, Olúwa,
    ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.

Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa,
    ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́,
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa;
    tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́,
    nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.

Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa:
    kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá
    yóò wá, láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa;
    wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu;
    ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.

11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa,
    èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ;
fún mi ní ọkàn tí kì í yapa,
    kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;
    èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi;
    ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú.

14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run;
    àti ìjọ àwọn alágbára ń wá
ọkàn mi kiri,
    wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere,
    Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi;
    fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára
    kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Fi ààmì hàn mí fún rere,
    kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri,
kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa
    ni ó ti tù mí nínú.

Psalm 86

A prayer of David.

Hear me, Lord, and answer(A) me,
    for I am poor and needy.
Guard my life, for I am faithful to you;
    save your servant who trusts in you.(B)
You are my God; have mercy(C) on me, Lord,
    for I call(D) to you all day long.
Bring joy to your servant, Lord,
    for I put my trust(E) in you.

You, Lord, are forgiving and good,
    abounding in love(F) to all who call to you.
Hear my prayer, Lord;
    listen to my cry(G) for mercy.
When I am in distress,(H) I call(I) to you,
    because you answer(J) me.

Among the gods(K) there is none like you,(L) Lord;
    no deeds can compare with yours.
All the nations you have made
    will come(M) and worship(N) before you, Lord;
    they will bring glory(O) to your name.
10 For you are great(P) and do marvelous deeds;(Q)
    you alone(R) are God.

11 Teach me your way,(S) Lord,
    that I may rely on your faithfulness;(T)
give me an undivided(U) heart,
    that I may fear(V) your name.
12 I will praise you, Lord my God, with all my heart;(W)
    I will glorify your name forever.
13 For great is your love toward me;
    you have delivered me(X) from the depths,
    from the realm of the dead.(Y)

14 Arrogant foes are attacking me, O God;
    ruthless people are trying to kill me—
    they have no regard for you.(Z)
15 But you, Lord, are a compassionate and gracious(AA) God,
    slow to anger,(AB) abounding(AC) in love and faithfulness.(AD)
16 Turn to me(AE) and have mercy(AF) on me;
    show your strength(AG) in behalf of your servant;
save me, because I serve you
    just as my mother did.(AH)
17 Give me a sign(AI) of your goodness,
    that my enemies may see it and be put to shame,
    for you, Lord, have helped me and comforted me.