Sekariah 9
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìdájọ́ lórí àwọn ọ̀tá Israẹli
9 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀:
Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki,
Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀;
nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn,
àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
2 Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀
Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
3 Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀,
ó sì kó fàdákà jọ bí eruku,
àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
4 Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ,
yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun,
a ó sì fi iná jó o run.
5 Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù;
Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi,
àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í.
Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀,
Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
6 Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu,
Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
7 Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀,
àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀:
ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa,
wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda,
àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
8 Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká
nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri,
kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́:
nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
Ọba sioni ń bọ̀
9 (A)Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu:
Wo ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ:
òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà;
ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
10 Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu,
àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu,
a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun.
Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí.
Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun,
àti láti odò títí de òpin ayé.
11 Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ,
Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
12 Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí:
àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
13 Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le,
mo sì fi Efraimu kún un,
Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni,
sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki,
mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
Olúwa yóò farahàn
14 Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn;
ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná.
Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè,
Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
15 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n;
wọn ó sì jẹ ni run,
wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀;
wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì,
wọn ó sì kún bí ọpọ́n,
wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
16 Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà
bí agbo ènìyàn rẹ̀:
nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé,
tí a gbé sókè bí ààmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀!
Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá,
àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Zechariah 9
New International Version
Judgment on Israel’s Enemies
9 A prophecy:(A)
The word of the Lord is against the land of Hadrak
and will come to rest on Damascus(B)—
for the eyes of all people and all the tribes of Israel
are on the Lord—[a]
2 and on Hamath(C) too, which borders on it,
and on Tyre(D) and Sidon,(E) though they are very skillful.
3 Tyre has built herself a stronghold;
she has heaped up silver like dust,
and gold like the dirt of the streets.(F)
4 But the Lord will take away her possessions
and destroy(G) her power on the sea,
and she will be consumed by fire.(H)
5 Ashkelon(I) will see it and fear;
Gaza will writhe in agony,
and Ekron too, for her hope will wither.
Gaza will lose her king
and Ashkelon will be deserted.
6 A mongrel people will occupy Ashdod,
and I will put an end(J) to the pride of the Philistines.
7 I will take the blood from their mouths,
the forbidden food from between their teeth.
Those who are left will belong to our God(K)
and become a clan in Judah,
and Ekron will be like the Jebusites.(L)
8 But I will encamp(M) at my temple
to guard it against marauding forces.(N)
Never again will an oppressor overrun my people,
for now I am keeping watch.(O)
The Coming of Zion’s King
9 Rejoice greatly, Daughter Zion!(P)
Shout,(Q) Daughter Jerusalem!
See, your king comes to you,(R)
righteous and victorious,(S)
lowly and riding on a donkey,(T)
on a colt, the foal of a donkey.(U)
10 I will take away the chariots from Ephraim
and the warhorses from Jerusalem,
and the battle bow will be broken.(V)
He will proclaim peace(W) to the nations.
His rule will extend from sea to sea
and from the River[b] to the ends of the earth.(X)
11 As for you, because of the blood of my covenant(Y) with you,
I will free your prisoners(Z) from the waterless pit.(AA)
12 Return to your fortress,(AB) you prisoners of hope;
even now I announce that I will restore twice(AC) as much to you.
13 I will bend Judah as I bend my bow(AD)
and fill it with Ephraim.(AE)
I will rouse your sons, Zion,
against your sons, Greece,(AF)
and make you like a warrior’s sword.(AG)
The Lord Will Appear
14 Then the Lord will appear over them;(AH)
his arrow will flash like lightning.(AI)
The Sovereign Lord will sound the trumpet;(AJ)
he will march in the storms(AK) of the south,
15 and the Lord Almighty will shield(AL) them.
They will destroy
and overcome with slingstones.(AM)
They will drink and roar as with wine;(AN)
they will be full like a bowl(AO)
used for sprinkling[c] the corners(AP) of the altar.
16 The Lord their God will save his people on that day(AQ)
as a shepherd saves his flock.
They will sparkle in his land
like jewels in a crown.(AR)
17 How attractive and beautiful they will be!
Grain will make the young men thrive,
and new wine the young women.
Footnotes
- Zechariah 9:1 Or Damascus. / For the eye of the Lord is on all people, / as well as on the tribes of Israel,
- Zechariah 9:10 That is, the Euphrates
- Zechariah 9:15 Or bowl, / like
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.