Add parallel Print Page Options

Peteru, aposteli Jesu Kristi,

Sí àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run, ti wọ́n ń ṣe àtìpó ní àgbáyé, tiwọn tú káàkiri sí Pọntu, Galatia, Kappadokia, Asia, àti Bitinia, àwọn ẹni tí a ti yàn gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run Baba, nípa ìsọdimímọ́ Ẹ̀mí, sí ìgbọ́ràn àti ìbùwọ́n ẹ̀jẹ̀ Jesu Kristi:

Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sì fún yín.

Ìyìn sí Ọlọ́run fún ìrètí tó wà láààyè

Ìyìn yẹ Ọlọ́run àti Baba Jesu Kristi Olúwa wa! Ẹni tí ó tún wa bí gẹ́gẹ́ bí àánú ńlá rẹ̀ sínú ìrètí ààyè nípa àjíǹde Jesu Kristi kúrò nínú òkú, àti sínú ogún àìdíbàjẹ́, àti àìlábàwọ́n, àti èyí tí kì í ṣá, tí a ti fi pamọ́ ni ọ̀run dè yin, ẹyin tí a ń pamọ́ nípa agbára Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ si ìgbàlà, tí a múra láti fihàn ní ìgbà ìkẹyìn. Ẹ yọ̀ nínú èyí púpọ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pe nísinsin yìí fún ìgbà díẹ̀, níwọ̀n bí ó ti yẹ, a ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdánwò bá yín nínú jẹ́: Àwọn wọ̀nyí sì wáyé ki ìdánwò ìgbàgbọ́ yín tí ó ni iye lórí ju wúrà, ti ń ṣègbé lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé iná ni a fi ń dán an wò, lè yọrísí ìyìn àti ògo àti ọlá ni ìgbà ìfarahàn Jesu Kristi. Ẹni tí ẹ̀yin fẹ́ láìrí, ẹni tí ẹ̀yin gbàgbọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ kò rí i nísinsin yìí ẹ̀yin sì ń yọ ayọ̀ tí a kò lè fi ẹnu sọ, tí ó sì kún fún ògo; ẹyin sì ń gba ìlépa ìgbàgbọ́ yín, àní ìgbàlà ọkàn yín.

10 Ní ti ìgbàlà yìí, àwọn wòlíì tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa oore-ọ̀fẹ́ tí ó mú tọ̀ yín wá, wọ́n wádìí jinlẹ̀ lẹ́sọ̀ lẹ́sọ̀. 11 Wọ́n ń wádìí ìgbà wo tàbí irú sá à wo ni Ẹ̀mí Kristi tí ó wà nínú wọ́n ń tọ́ka sí, nígbà tí ó jẹ́rìí ìyà Kristi àti ògo tí yóò tẹ̀lé e. 12 Àwọn ẹni tí a fihàn fún, pé kì í ṣe fún àwọn tìkára wọn, bí kò ṣe fún àwa ni wọ́n ṣe ìránṣẹ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti ròyìn fún yin nísinsin yìí, láti ọ̀dọ̀ àwọn tó ti ń wàásù ìhìnrere náà fún yín nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ tí a rán wá láti ọ̀run; ohun tí àwọn angẹli ń fẹ́ láti wò.

Ẹ jẹ́ mímọ́

13 Nítorí náà, ẹ múra ọkàn yín sílẹ̀, ẹ kó ara yín ní ìjánu, kí ẹ sì fi ìrètí yín ní kíkún sí oore-ọ̀fẹ́, èyí tí a ń mu bọ̀ fún yin ni ìgbà ìfarahàn Jesu Kristi. 14 Bí àwọn ọmọ tí ń gbọ́rọ̀, ẹ ma ṣe da ara yín pọ̀ mọ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àìmọ́ yín ti àtijọ́. 15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹni tí o pè yin ti jẹ mímọ́; bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà jẹ mímọ́. 16 (A)Nítorí a ti kọ ọ pé, “Ẹ jẹ́ mímọ́: nítorí tí Èmi jẹ mímọ́!”

17 Níwọ́n bí ẹ̀yin ti ń ké pe Baba, ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ olúkúlùkù láìṣe ojúsàájú, ẹ máa lo ìgbà àtìpó yin ni ìbẹ̀rù. 18 Níwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé a kò fi ohun ìdíbàjẹ́ rà yín padà, bí fàdákà tàbí wúrà kúrò nínú ìwà asán yín, tí ẹ̀yin ti jogún láti ọ̀dọ̀ àwọn baba yín. 19 Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ iyebíye, bí i ti ọ̀dọ́-àgùntàn ti kò lábùkù, tí kò sì lábàwọ́n, àní, ẹ̀jẹ̀ Kristi. 20 Ẹni tí a ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ nítòótọ́ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, ṣùgbọ́n tí a fihàn ní ìgbà ìkẹyìn wọ̀nyí nítorí yín, 21 Àní ẹ̀yin tí o tipasẹ̀ rẹ̀ gba Ọlọ́run gbọ́, ẹni ti ó jí i dìde kúrò nínú òkú, tí ó sì fi ògo fún un; kí ìgbàgbọ́ àti ìrètí yín lè wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

22 Níwọ́n bí ẹ̀yin ti wẹ ọkàn yin mọ́ nípa ìgbọ́ràn yín sí òtítọ́ sí ìfẹ́ ará ti kò ní ẹ̀tàn, ẹ fẹ́ ọmọnìkejì yín gidigidi láti ọkàn wá. 23 Bí a ti tún yín bí, kì í ṣe láti inú ìdíbàjẹ́ wá, bí kò ṣe èyí ti kì í díbàjẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ń bẹ láààyè tí ó sì dúró. 24 (B)Nítorí pé,

“Gbogbo ènìyàn dàbí koríko,
    àti gbogbo ògo rẹ̀ bi ìtànná koríko.
Koríko á máa gbẹ ìtànná a sì máa rẹ̀ dànù,
25     Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa dúró títí láé.”

Ọ̀rọ̀ náà yìí sì ni ìhìnrere tí a wàásù fún yín.

Peter, an apostle of Jesus Christ,(A)

To God’s elect,(B) exiles(C) scattered(D) throughout the provinces of Pontus,(E) Galatia,(F) Cappadocia, Asia and Bithynia,(G) who have been chosen according to the foreknowledge(H) of God the Father, through the sanctifying work of the Spirit,(I) to be obedient(J) to Jesus Christ and sprinkled with his blood:(K)

Grace and peace be yours in abundance.(L)

Praise to God for a Living Hope

Praise be to the God and Father of our Lord Jesus Christ!(M) In his great mercy(N) he has given us new birth(O) into a living hope(P) through the resurrection of Jesus Christ from the dead,(Q) and into an inheritance(R) that can never perish, spoil or fade.(S) This inheritance is kept in heaven for you,(T) who through faith are shielded by God’s power(U) until the coming of the salvation(V) that is ready to be revealed(W) in the last time. In all this you greatly rejoice,(X) though now for a little while(Y) you may have had to suffer grief in all kinds of trials.(Z) These have come so that the proven genuineness(AA) of your faith—of greater worth than gold, which perishes even though refined by fire(AB)—may result in praise, glory and honor(AC) when Jesus Christ is revealed.(AD) Though you have not seen him, you love him; and even though you do not see him now, you believe in him(AE) and are filled with an inexpressible and glorious joy, for you are receiving the end result of your faith, the salvation of your souls.(AF)

10 Concerning this salvation, the prophets, who spoke(AG) of the grace that was to come to you,(AH) searched intently and with the greatest care,(AI) 11 trying to find out the time and circumstances to which the Spirit of Christ(AJ) in them was pointing when he predicted(AK) the sufferings of the Messiah and the glories that would follow. 12 It was revealed to them that they were not serving themselves but you,(AL) when they spoke of the things that have now been told you by those who have preached the gospel to you(AM) by the Holy Spirit sent from heaven.(AN) Even angels long to look into these things.

Be Holy

13 Therefore, with minds that are alert and fully sober,(AO) set your hope(AP) on the grace to be brought to you(AQ) when Jesus Christ is revealed at his coming.(AR) 14 As obedient(AS) children, do not conform(AT) to the evil desires you had when you lived in ignorance.(AU) 15 But just as he who called you is holy, so be holy in all you do;(AV) 16 for it is written: “Be holy, because I am holy.”[a](AW)

17 Since you call on a Father(AX) who judges each person’s work(AY) impartially,(AZ) live out your time as foreigners(BA) here in reverent fear.(BB) 18 For you know that it was not with perishable things such as silver or gold that you were redeemed(BC) from the empty way of life(BD) handed down to you from your ancestors, 19 but with the precious blood(BE) of Christ, a lamb(BF) without blemish or defect.(BG) 20 He was chosen before the creation of the world,(BH) but was revealed in these last times(BI) for your sake. 21 Through him you believe in God,(BJ) who raised him from the dead(BK) and glorified him,(BL) and so your faith and hope(BM) are in God.

22 Now that you have purified(BN) yourselves by obeying(BO) the truth so that you have sincere love for each other, love one another deeply,(BP) from the heart.[b] 23 For you have been born again,(BQ) not of perishable seed, but of imperishable,(BR) through the living and enduring word of God.(BS) 24 For,

“All people are like grass,
    and all their glory is like the flowers of the field;
the grass withers and the flowers fall,
25     but the word of the Lord endures forever.”[c](BT)

And this is the word that was preached to you.

Footnotes

  1. 1 Peter 1:16 Lev. 11:44,45; 19:2
  2. 1 Peter 1:22 Some early manuscripts from a pure heart
  3. 1 Peter 1:25 Isaiah 40:6-8 (see Septuagint)