Amosi 1
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
1 Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 (A)Ó wí pé:
“Olúwa yóò bú jáde láti Sioni
ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;
Ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,
orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli
3 (B)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.
Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú
4 Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli
Èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;
Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní Àfonífojì Afeni run
àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.
Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”
ni Olúwa wí.
6 (C)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,
àní nítorí mẹ́rin,
Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,
ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.
Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa
tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run
8 Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,
ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.
Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni
títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”
ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 (D)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu
Wọn kò sì nání májẹ̀mú ọbàkan,
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire
Tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 (E)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,
Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù
ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí
ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani
Tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 (F)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
ni Olúwa wí.
Amos 1
New International Version
1 The words of Amos, one of the shepherds of Tekoa(A)—the vision he saw concerning Israel two years before the earthquake,(B) when Uzziah(C) was king of Judah and Jeroboam(D) son of Jehoash[a] was king of Israel.(E)
2 He said:
“The Lord roars(F) from Zion
and thunders(G) from Jerusalem;(H)
the pastures of the shepherds dry up,
and the top of Carmel(I) withers.”(J)
Judgment on Israel’s Neighbors
3 This is what the Lord says:
“For three sins of Damascus,(K)
even for four, I will not relent.(L)
Because she threshed Gilead
with sledges having iron teeth,
4 I will send fire(M) on the house of Hazael(N)
that will consume the fortresses(O) of Ben-Hadad.(P)
5 I will break down the gate(Q) of Damascus;
I will destroy the king who is in[b] the Valley of Aven[c]
and the one who holds the scepter in Beth Eden.(R)
The people of Aram will go into exile to Kir,(S)”
says the Lord.(T)
6 This is what the Lord says:
“For three sins of Gaza,(U)
even for four, I will not relent.(V)
Because she took captive whole communities
and sold them to Edom,(W)
7 I will send fire on the walls of Gaza
that will consume her fortresses.
8 I will destroy the king[d] of Ashdod(X)
and the one who holds the scepter in Ashkelon.
I will turn my hand(Y) against Ekron,
till the last of the Philistines(Z) are dead,”(AA)
says the Sovereign Lord.(AB)
9 This is what the Lord says:
“For three sins of Tyre,(AC)
even for four, I will not relent.(AD)
Because she sold whole communities of captives to Edom,
disregarding a treaty of brotherhood,(AE)
10 I will send fire on the walls of Tyre
that will consume her fortresses.(AF)”
11 This is what the Lord says:
“For three sins of Edom,(AG)
even for four, I will not relent.
Because he pursued his brother with a sword(AH)
and slaughtered the women of the land,
because his anger raged continually
and his fury flamed unchecked,(AI)
12 I will send fire on Teman(AJ)
that will consume the fortresses of Bozrah.(AK)”
13 This is what the Lord says:
“For three sins of Ammon,(AL)
even for four, I will not relent.
Because he ripped open the pregnant women(AM) of Gilead
in order to extend his borders,
14 I will set fire to the walls of Rabbah(AN)
that will consume(AO) her fortresses
amid war cries(AP) on the day of battle,
amid violent winds(AQ) on a stormy day.
15 Her king[e] will go into exile,
he and his officials together,(AR)”
says the Lord.(AS)
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.