Add parallel Print Page Options

Pẹpẹ ní orí òkè Ebali

27 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé: “Pa gbogbo àṣẹ tí mo fún ọ lónìí mọ́. Nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani sí inú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, gbé kalẹ̀ lára àwọn òkúta ńlá àti aṣọ ìlekè rẹ pẹ̀lú ẹfun. Kí ìwọ kí ó kọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí sára wọn nígbà tí ìwọ bá ti ń rékọjá láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti ṣèlérí fún ọ. Àti nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani, kí o gbé òkúta yìí kalẹ̀ sórí i Ebali, bí mo ti pa à láṣẹ fún ọ lónìí, kí o sì wọ̀ wọ́n pẹ̀lú ẹfun. Kọ́ pẹpẹ síbẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, pẹpẹ òkúta. Má ṣe lo ohun èlò irin lórí wọn. Kí ìwọ kí ó mọ pẹpẹ pẹ̀lú òkúta àìgbẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí ìwọ kí ó sì máa rú ẹbọ sísun ni orí rẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ. Rú ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀ kí o jẹ wọ́n, kí o sì yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ. Kí o sì kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí ketekete sórí òkúta tí ó ti gbé kalẹ̀.”

Ègún ní orí òkè Ebali

Nígbà náà ni Mose àti àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, sọ fún Israẹli pé, “Ẹ dákẹ́ ẹ̀yin Israẹli, kí ẹ sì fetísílẹ̀! O ti wá di ènìyàn Olúwa Ọlọ́run rẹ báyìí. 10 Gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì tẹ̀lé àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mo ń fi fún ọ lónìí.”

11 Ní ọjọ́ kan náà Mose pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé.

12 Nígbà tí ìwọ bá ti kọjá a Jordani, àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Gerisimu láti súre fún àwọn ènìyàn: Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Josẹfu àti Benjamini. 13 Àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Ebali láti gé ègún: Reubeni, Gadi, àti Aṣeri, àti Sebuluni, Dani, àti Naftali.

14 Àwọn ẹ̀yà Lefi yóò ké sí gbogbo ènìyàn Israẹli ní ohùn òkè:

15 (A)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó fín ère tàbí gbẹ́ òrìṣà ohun tí ó jẹ́ ìríra níwájú Olúwa, iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà tí ó gbé kalẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

16 (B)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dójútì baba tàbí ìyá rẹ̀”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

17 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí òkúta ààlà aládùúgbò o rẹ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

18 (C)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣi afọ́jú lọ́nà ní ojú ọ̀nà.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

19 (D)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí ìdájọ́ po fún àlejò, aláìní baba tàbí opó”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

20 (E)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó baba rẹ̀, nítorí ó ti dójúti ibùsùn baba rẹ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

21 (F)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹranko.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

22 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú arábìnrin rẹ̀, ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

23 (G)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyá ìyàwó o rẹ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

24 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

25 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti pa ènìyàn láìjẹ̀bi.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

26 (H)“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí kò gbé ọ̀rọ̀ òfin yìí ró nípa ṣíṣe wọ́n.”

Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

The Altar on Mount Ebal

27 Moses and the elders of Israel commanded the people: “Keep all these commands(A) that I give you today. When you have crossed the Jordan(B) into the land the Lord your God is giving you, set up some large stones(C) and coat them with plaster.(D) Write on them all the words of this law when you have crossed over to enter the land the Lord your God is giving you, a land flowing with milk and honey,(E) just as the Lord, the God of your ancestors, promised you. And when you have crossed the Jordan, set up these stones on Mount Ebal,(F) as I command you today, and coat them with plaster. Build there an altar(G) to the Lord your God, an altar of stones. Do not use any iron tool(H) on them. Build the altar of the Lord your God with fieldstones and offer burnt offerings on it to the Lord your God. Sacrifice fellowship offerings(I) there, eating them and rejoicing(J) in the presence of the Lord your God.(K) And you shall write very clearly all the words of this law on these stones(L) you have set up.”(M)

Curses From Mount Ebal

Then Moses and the Levitical(N) priests said to all Israel, “Be silent, Israel, and listen! You have now become the people of the Lord your God.(O) 10 Obey the Lord your God and follow his commands and decrees that I give you today.”

11 On the same day Moses commanded the people:

12 When you have crossed the Jordan, these tribes shall stand on Mount Gerizim(P) to bless the people: Simeon, Levi, Judah, Issachar,(Q) Joseph and Benjamin.(R) 13 And these tribes shall stand on Mount Ebal(S) to pronounce curses: Reuben, Gad, Asher, Zebulun, Dan and Naphtali.

14 The Levites shall recite to all the people of Israel in a loud voice:

15 “Cursed is anyone who makes an idol(T)—a thing detestable(U) to the Lord, the work of skilled hands—and sets it up in secret.”

Then all the people shall say, “Amen!”(V)

16 “Cursed is anyone who dishonors their father or mother.”(W)

Then all the people shall say, “Amen!”

17 “Cursed is anyone who moves their neighbor’s boundary stone.”(X)

Then all the people shall say, “Amen!”

18 “Cursed is anyone who leads the blind astray on the road.”(Y)

Then all the people shall say, “Amen!”

19 “Cursed is anyone who withholds justice from the foreigner,(Z) the fatherless or the widow.”(AA)

Then all the people shall say, “Amen!”

20 “Cursed is anyone who sleeps with his father’s wife, for he dishonors his father’s bed.”(AB)

Then all the people shall say, “Amen!”

21 “Cursed is anyone who has sexual relations with any animal.”(AC)

Then all the people shall say, “Amen!”

22 “Cursed is anyone who sleeps with his sister, the daughter of his father or the daughter of his mother.”(AD)

Then all the people shall say, “Amen!”

23 “Cursed is anyone who sleeps with his mother-in-law.”(AE)

Then all the people shall say, “Amen!”

24 “Cursed is anyone who kills(AF) their neighbor secretly.”(AG)

Then all the people shall say, “Amen!”

25 “Cursed is anyone who accepts a bribe to kill an innocent person.”(AH)

Then all the people shall say, “Amen!”

26 “Cursed is anyone who does not uphold the words of this law by carrying them out.”(AI)

Then all the people shall say, “Amen!”(AJ)