Add parallel Print Page Options

Ìdáàbòbò ohun ìní

22 “Bí ọkùnrin kan bá jí akọ màlúù tàbí àgùntàn, tí ó sì pa á tàbí tà á. Ó gbọdọ̀ san akọ màlúù márùn-ún padà fún ọ̀kan tí ó jí, àti àgùntàn mẹ́rin mìíràn fún ọ̀kan tí ó jí.

“Bí a bá mú olè níbi ti ó ti ń fọ́lé, ti a sì lù ú pa, ẹni tí ó lù ú pa náà kò ní ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀. Ṣùgbọ́n ti ó bá ṣẹlẹ̀ ni ojú ọ̀sán, a ó kà á si ìpànìyàn. Ọkùnrin ti ó lù ú pa náà yóò ni ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀.

“Olè gbọdọ̀ san ohun tí ó jí padà. Ṣùgbọ́n tí kò bá ni ohun ti ó lè fi san án padà, a ó tà á, a ó sì fi sanwó ohun tí ó jí gbé padà. Bí a bá rí ẹran tí ó jí gbé náà ni ọwọ́ rẹ̀ ní ààyè: ìbá ṣe akọ màlúù, akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àgùntàn, yóò san án padà ní ìlọ́po méjì.

“Bí ọkùnrin kan bá ń bọ́ ẹran ọ̀sìn rẹ̀ lórí pápá tàbí nínú ọgbà àjàrà, tí ó sì jẹ́ kí ó lọ jẹ nínú oko ẹlòmíràn, a ó mú kí ó san ohun ti ẹran rẹ̀ jẹ padà pẹ̀lú èyí tí ó dára jù nínú oko tàbí nínú ọgbà rẹ̀ (ẹlòmíràn padà fún un).

“Bí iná bá ṣẹ́ tí ó kán lu igbó tí ó sì jó àká ọkà tàbí gbogbo oko náà, ẹni tí iná ṣẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀ yóò san ohun tí iná ti ó ṣẹ́ jó padà.

(A)“Bí ọkùnrin kan bá fún aládùúgbò rẹ̀ ní fàdákà tàbí ohun èlò fún ìtọ́jú, ti wọ́n sì jí gbé lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí a bá mú irú olè bẹ́ẹ̀, yóò san án padà ní ìlọ́po méjì. Ṣùgbọ́n ti a kò bá rí olè náà mú, baálé ilé náà yóò fi ara hàn níwájú ìdájọ́ láti jẹ́ kí a mọ̀ bí òun fúnrarẹ̀ ni ó gbé ohun ti ó sọnù náà. Bí ẹnìkan bá ni akọ màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, aṣọ tàbí ohun ìní mìíràn tí ó sọnù ní ọ̀nà ti kò bá òfin mu, tí a sì rí ẹni ti ó sọ pé òun ni ó ní ín, àwọn méjèèjì yóò mú ẹjọ́ wọn wá sí iwájú adájọ́. Ẹnikẹ́ni tí adájọ́ bá dá lẹ́bi yóò san án ni ìlọ́po méjì padà fún ẹnìkejì rẹ̀.

10 “Bí ẹnikẹ́ni bá fún aládùúgbò rẹ̀ ní kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, akọ màlúù, àgùntàn tàbí ẹranko mìíràn láti bá òun tọ́jú rẹ̀, tí ó sì kú, tàbí tí ó fi ara pa, tàbí tí a jí gbé, níbi tí kò ti sí ẹni tí o ṣe àkíyèsí. 11 Wọn yóò búra sí ọ̀rọ̀ náà láàrín ara wọn ni iwájú Olúwa láti fihàn pé òun kò ní ọwọ́ nínú sísọnù ohun ọ̀sìn náà, olóhun gbọdọ̀ gba bẹ́ẹ̀, a kò sì ní san ohunkóhun fún un. 12 Ṣùgbọ́n ti wọ́n bá jí ẹranko náà gbé ni ọ̀dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, yóò san ẹ̀san padà fún olúwa rẹ̀. 13 Bí ẹranko búburú bá fà á ya, ó ní láti mú àyakù ẹran náà wá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí, kò sì ní san ẹran náà padà.

14 “Bí ẹnìkan bá sì yá ẹranko lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ẹranko náà sì fi ara pa, tàbí kí ó kú nígbà tí ẹni tí ó ni í kò sí nítòsí. O gbọdọ̀ san án padà. 15 Ṣùgbọ́n ti ó bá jẹ́ wí pé olóhun bá wà pẹ̀lú ẹranko náà, ẹni tí ó ya lò kò ní san ẹ̀san padà. Bí a bá yá ẹranko náà lò, owó tí ó fi yá a lò ni yóò fi tan àdánù ẹranko tí ó kú.

Ìlànà ojúṣe ẹni láwùjọ

16 (B)“Bí ọkùnrin kan bá fi àrékérekè mú wúńdíá kan, ẹni tí kò pinnu láti fẹ́, tí ó sì bá a lòpọ̀, yóò san owó orí rẹ̀, yóò sì fi ṣe aya rẹ̀. 17 Bí baba ọmọbìnrin náà bá kọ̀ jálẹ̀ láti fi fún un ní aya, ó ni láti san owó tó tó owó orí rẹ̀ fún fífẹ́ ẹ ní wúńdíá.

18 (C)“Má ṣe jẹ́ kí àjẹ́ kí ó wà láààyè.

19 (D)“Ẹnikẹ́ni ti ó bá bá ẹranko lòpọ̀ ní a ó pa.

20 “Ẹnikẹ́ni ti ó bá rú ẹbọ sí òrìṣà yàtọ̀ sí Olúwa nìkan, ni a ó yà sọ́tọ̀ fún ìparun.

21 (E)“Ẹ má ṣe fi ìyà jẹ àlejò tàbí ni wọ́n lára, nítorí ìwọ pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì ni ilẹ̀ Ejibiti rí.

22 (F)“Má ṣe yan opó tàbí ọmọ òrukàn jẹ. 23 Bí ìwọ bá ṣe bẹ́ẹ̀, bí wọn bá ké pè mi. Èmi yóò sì gbọ́ ohùn igbe wọn. 24 Ìbínú mi yóò ru sókè. Èmi yóò sì fi idà pa ọ. Ìyàwó rẹ yóò di opó, àwọn ọmọ rẹ yóò sì di aláìní baba.

25 (G)“Bí ìwọ bá yá ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn mi tí ìyà ń jẹ láàrín yín lówó, má ṣe dàbí ayánilówó, kí o má sì gba èlé. 26 (H)Bí ìwọ bá gba aṣọ aládùúgbò rẹ ni ẹ̀jẹ́, ìwọ gbọdọ̀ fún un padà kí oòrùn tó ó wọ̀, 27 Nítorí aṣọ yìí nìkan ní ó ní ti ó lè fi bo àṣírí ara. Kí ni ohun mìíràn ti yóò fi sùn? Nígbà ti ó bá gbé ohun rẹ̀ sókè sí mi, èmi yóò gbọ́ nítorí aláàánú ni èmi.

28 (I)“Ìwọ kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run tàbí gégùn lé orí ìjòyè àwọn ènìyàn rẹ.

29 (J)“Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ́ra láti mú ọrẹ wá fún mi láti inú ìre oko rẹ àti láti inú wáìnì rẹ.

“Àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin ni ìwọ yóò fi fún mi. 30 Ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú agbo màlúù rẹ àti agbo àgùntàn rẹ. Jẹ́ kí wọn wà lọ́dọ̀ ìyá wọn fún ọjọ́ méje, kí ìwọ kí ó sì fi wọ́n fún mi ní ọjọ́ kẹjọ.

31 (K)“Ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mímọ́ mi. Nítorí náà má ṣe jẹ ẹran ti ẹranko búburú fàya: ẹ fi fún ajá jẹ.

Protection of Property

22 [a]“Whoever steals an ox or a sheep and slaughters it or sells it must pay back(A) five head of cattle for the ox and four sheep for the sheep.

“If a thief is caught breaking in(B) at night and is struck a fatal blow, the defender is not guilty of bloodshed;(C) but if it happens after sunrise, the defender is guilty of bloodshed.

“Anyone who steals must certainly make restitution,(D) but if they have nothing, they must be sold(E) to pay for their theft. If the stolen animal is found alive in their possession(F)—whether ox or donkey or sheep—they must pay back double.(G)

“If anyone grazes their livestock in a field or vineyard and lets them stray and they graze in someone else’s field, the offender must make restitution(H) from the best of their own field or vineyard.

“If a fire breaks out and spreads into thornbushes so that it burns shocks(I) of grain or standing grain or the whole field, the one who started the fire must make restitution.(J)

“If anyone gives a neighbor silver or goods for safekeeping(K) and they are stolen from the neighbor’s house, the thief, if caught, must pay back double.(L) But if the thief is not found, the owner of the house must appear before the judges,(M) and they must[b] determine whether the owner of the house has laid hands on the other person’s property. In all cases of illegal possession of an ox, a donkey, a sheep, a garment, or any other lost property about which somebody says, ‘This is mine,’ both parties are to bring their cases before the judges.[c](N) The one whom the judges declare[d] guilty must pay back double to the other.

10 “If anyone gives a donkey, an ox, a sheep or any other animal to their neighbor for safekeeping(O) and it dies or is injured or is taken away while no one is looking, 11 the issue between them will be settled by the taking of an oath(P) before the Lord that the neighbor did not lay hands on the other person’s property. The owner is to accept this, and no restitution is required. 12 But if the animal was stolen from the neighbor, restitution(Q) must be made to the owner. 13 If it was torn to pieces by a wild animal, the neighbor shall bring in the remains as evidence and shall not be required to pay for the torn animal.(R)

14 “If anyone borrows an animal from their neighbor and it is injured or dies while the owner is not present, they must make restitution.(S) 15 But if the owner is with the animal, the borrower will not have to pay. If the animal was hired, the money paid for the hire covers the loss.(T)

Social Responsibility

16 “If a man seduces a virgin(U) who is not pledged to be married and sleeps with her, he must pay the bride-price,(V) and she shall be his wife. 17 If her father absolutely refuses to give her to him, he must still pay the bride-price for virgins.

18 “Do not allow a sorceress(W) to live.

19 “Anyone who has sexual relations with an animal(X) is to be put to death.

20 “Whoever sacrifices to any god(Y) other than the Lord must be destroyed.[e](Z)

21 “Do not mistreat or oppress a foreigner,(AA) for you were foreigners(AB) in Egypt.

22 “Do not take advantage of the widow or the fatherless.(AC) 23 If you do and they cry out(AD) to me, I will certainly hear their cry.(AE) 24 My anger will be aroused, and I will kill you with the sword; your wives will become widows and your children fatherless.(AF)

25 “If you lend money to one of my people among you who is needy, do not treat it like a business deal; charge no interest.(AG) 26 If you take your neighbor’s cloak as a pledge,(AH) return it by sunset, 27 because that cloak is the only covering your neighbor has. What else can they sleep in?(AI) When they cry out to me, I will hear, for I am compassionate.(AJ)

28 “Do not blaspheme God[f](AK) or curse(AL) the ruler of your people.(AM)

29 “Do not hold back offerings(AN) from your granaries or your vats.[g]

“You must give me the firstborn of your sons.(AO) 30 Do the same with your cattle and your sheep.(AP) Let them stay with their mothers for seven days, but give them to me on the eighth day.(AQ)

31 “You are to be my holy people.(AR) So do not eat the meat of an animal torn by wild beasts;(AS) throw it to the dogs.

Footnotes

  1. Exodus 22:1 In Hebrew texts 22:1 is numbered 21:37, and 22:2-31 is numbered 22:1-30.
  2. Exodus 22:8 Or before God, and he will
  3. Exodus 22:9 Or before God
  4. Exodus 22:9 Or whom God declares
  5. Exodus 22:20 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them.
  6. Exodus 22:28 Or Do not revile the judges
  7. Exodus 22:29 The meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.