Add parallel Print Page Options

28 (A)“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn:

“ ‘Idà kan idà kan
    tí á fa yọ fún ìpànìyàn
tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò
    àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín
    àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín
a yóò gbé e lé àwọn ọrùn
    ènìyàn búburú ti a ó pa,
àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé,
    àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.

30 “ ‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀
    Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín,
    ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín,
    èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná
    mi bá yín jà.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà,
    a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín,
a kì yóò rántí yín mọ́;
    nítorí èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’ ”

Read full chapter

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Ammoni

25 (A)Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn. Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé: Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn, kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ: wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ. Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”

Read full chapter

13 (A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
    àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
    kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
    pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
    Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
    ni Olúwa wí.

Read full chapter

Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni

(A)“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
    àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
    tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
    “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
    ibi tí ó kún fún yèrèpè
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
    Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni
    yóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
    nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
    nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
    olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.

Read full chapter