Add parallel Print Page Options

28 (A)“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn:

“ ‘Idà kan idà kan
    tí á fa yọ fún ìpànìyàn
tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò
    àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín
    àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín
a yóò gbé e lé àwọn ọrùn
    ènìyàn búburú ti a ó pa,
àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé,
    àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.

30 “ ‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀
    Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín,
    ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín,
    èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná
    mi bá yín jà.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà,
    a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín,
a kì yóò rántí yín mọ́;
    nítorí èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’ ”

Read full chapter

Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Ammoni

49 (A)Ní ti Ammoni:

Báyìí ni Olúwa wí:

“Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin?
    Israẹli kò ha ní àrólé bí?
Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi?
    Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,”
    ni Olúwa wí;
“nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba
    tí Ammoni yóò sì di òkìtì ahoro,
gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná.
    Nígbà náà ni Israẹli yóò
lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,”
    ni Olúwa wí.
“Hu, ìwọ Heṣboni
    nítorí Ai tí rún,
kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba!
    Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀.
Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà,
    nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn
    pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú Àfonífojì rẹ,
    ṣògo nínú Àfonífojì rẹ fún èso?
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́,
    ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé,
    ‘ta ni yóò kò mí lójú?’
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ
    láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,”
    ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
    Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan
tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,”
    ni Olúwa wí.

Read full chapter

13 (A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
    àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
    kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
    pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
    Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
    ni Olúwa wí.

Read full chapter

Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni

(A)“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
    àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
    tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
    “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
    ibi tí ó kún fún yèrèpè
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
    Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni
    yóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
    nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
    nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
    olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.

Read full chapter