Add parallel Print Page Options

Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.” Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.

Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.

Ó sì tún sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli. A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ. Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli. Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le. Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”

10 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ. 11 Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”

12 Nígbà náà ni Ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá! 13 Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá. 14 Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi. 15 Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.

Ìkìlọ̀ sí Israẹli

16 (A)Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: 17 “Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi. 18 Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. 19 Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.

20 “Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. 21 Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”

22 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.” 23 Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.

24 Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé: “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ 25 ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn. 26 Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn 27 Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

And he said to me, “Son of man, eat what is before you, eat this scroll; then go and speak to the people of Israel.” So I opened my mouth, and he gave me the scroll to eat.

Then he said to me, “Son of man, eat this scroll I am giving you and fill your stomach with it.” So I ate(A) it, and it tasted as sweet as honey(B) in my mouth.

He then said to me: “Son of man, go now to the people of Israel and speak my words to them.(C) You are not being sent to a people of obscure speech and strange language,(D) but to the people of Israel— not to many peoples of obscure speech and strange language, whose words you cannot understand. Surely if I had sent you to them, they would have listened to you.(E) But the people of Israel are not willing to listen(F) to you because they are not willing to listen to me, for all the Israelites are hardened and obstinate.(G) But I will make you as unyielding and hardened as they are.(H) I will make your forehead(I) like the hardest stone, harder than flint.(J) Do not be afraid of them or terrified by them, though they are a rebellious people.(K)

10 And he said to me, “Son of man, listen carefully and take to heart(L) all the words I speak to you. 11 Go(M) now to your people in exile and speak to them. Say to them, ‘This is what the Sovereign Lord says,’(N) whether they listen or fail to listen.(O)

12 Then the Spirit lifted me up,(P) and I heard behind me a loud rumbling sound as the glory of the Lord rose from the place where it was standing.[a] 13 It was the sound of the wings of the living creatures(Q) brushing against each other and the sound of the wheels beside them, a loud rumbling sound.(R) 14 The Spirit(S) then lifted me up(T) and took me away, and I went in bitterness and in the anger of my spirit, with the strong hand of the Lord(U) on me. 15 I came to the exiles who lived at Tel Aviv near the Kebar River.(V) And there, where they were living, I sat among them for seven days(W)—deeply distressed.

Ezekiel’s Task as Watchman

16 At the end of seven days the word of the Lord came to me:(X) 17 “Son of man, I have made you a watchman(Y) for the people of Israel; so hear the word I speak and give them warning from me.(Z) 18 When I say to a wicked person, ‘You will surely die,(AA)’ and you do not warn them or speak out to dissuade them from their evil ways in order to save their life, that wicked person will die for[b] their sin, and I will hold you accountable for their blood.(AB) 19 But if you do warn the wicked person and they do not turn(AC) from their wickedness(AD) or from their evil ways, they will die(AE) for their sin; but you will have saved yourself.(AF)

20 “Again, when a righteous person turns(AG) from their righteousness and does evil, and I put a stumbling block(AH) before them, they will die. Since you did not warn them, they will die for their sin. The righteous things that person did will not be remembered, and I will hold you accountable for their blood.(AI) 21 But if you do warn the righteous person not to sin and they do not sin, they will surely live because they took warning, and you will have saved yourself.(AJ)

22 The hand of the Lord(AK) was on me there, and he said to me, “Get up and go(AL) out to the plain,(AM) and there I will speak to you.” 23 So I got up and went out to the plain. And the glory of the Lord was standing there, like the glory I had seen by the Kebar River,(AN) and I fell facedown.(AO)

24 Then the Spirit came into me and raised me(AP) to my feet. He spoke to me and said: “Go, shut yourself inside your house.(AQ) 25 And you, son of man, they will tie with ropes; you will be bound so that you cannot go out among the people.(AR) 26 I will make your tongue stick to the roof(AS) of your mouth so that you will be silent and unable to rebuke them, for they are a rebellious people.(AT) 27 But when I speak to you, I will open your mouth and you shall say to them, ‘This is what the Sovereign Lord says.’(AU) Whoever will listen let them listen, and whoever will refuse let them refuse; for they are a rebellious people.(AV)

Footnotes

  1. Ezekiel 3:12 Probable reading of the original Hebrew text; Masoretic Text sound—may the glory of the Lord be praised from his place
  2. Ezekiel 3:18 Or in; also in verses 19 and 20