Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Jakọbu sí àwọn ọmọ rẹ̀

49 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.

“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu;
    Ẹ fetí sí Israẹli baba yín.

“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi,
    agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi,
    títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́,
    nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ,
    lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́
(ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).

“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin—
    idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn,
    kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn,
nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn,
    wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó
    gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà.
Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu,
    èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.

“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,
    ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ,
    àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
(A)Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda,
    o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi.
Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,
    Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda
    bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀,
títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé,
    tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà,
    àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.
Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì
    àti ẹ̀wù rẹ̀ nù nínú omi-pupa ti èso àjàrà (gireepu).
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,
    eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.

13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun,
    yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,
    agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.

14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára
    tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,
    àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó,
yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà,
    yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.

16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà
    àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,
tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀,
    kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.

18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.

19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi,
    ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.

20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára;
    yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.

21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín
    tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.

22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso,
    àjàrà eléso ní etí odò,
    tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́,
    wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra,
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára,
    ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le,
nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu,
    nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́,
    nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ
pẹ̀lú láti ọ̀run wá,
    ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀,
    ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀
    ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì,
    ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé.
Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu,
    lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.

27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú;
    ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ,
    ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”

28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.

Ikú Jakọbu

29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni. 30 (B)Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀. 31 (C)Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí. 32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”

33 (D)Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.

Jacob Blesses His Sons(A)

49 Then Jacob called for his sons and said: “Gather around so I can tell you what will happen to you in days to come.(B)

“Assemble(C) and listen, sons of Jacob;
    listen to your father Israel.(D)

“Reuben, you are my firstborn,(E)
    my might, the first sign of my strength,(F)
    excelling in honor,(G) excelling in power.
Turbulent as the waters,(H) you will no longer excel,
    for you went up onto your father’s bed,
    onto my couch and defiled it.(I)

“Simeon(J) and Levi(K) are brothers—
    their swords[a] are weapons of violence.(L)
Let me not enter their council,
    let me not join their assembly,(M)
for they have killed men in their anger(N)
    and hamstrung(O) oxen as they pleased.
Cursed be their anger, so fierce,
    and their fury,(P) so cruel!(Q)
I will scatter them in Jacob
    and disperse them in Israel.(R)

“Judah,[b](S) your brothers will praise you;
    your hand will be on the neck(T) of your enemies;
    your father’s sons will bow down to you.(U)
You are a lion’s(V) cub,(W) Judah;(X)
    you return from the prey,(Y) my son.
Like a lion he crouches and lies down,
    like a lioness—who dares to rouse him?
10 The scepter will not depart from Judah,(Z)
    nor the ruler’s staff from between his feet,[c]
until he to whom it belongs[d] shall come(AA)
    and the obedience of the nations shall be his.(AB)
11 He will tether his donkey(AC) to a vine,
    his colt to the choicest branch;(AD)
he will wash his garments in wine,
    his robes in the blood of grapes.(AE)
12 His eyes will be darker than wine,
    his teeth whiter than milk.[e](AF)

13 “Zebulun(AG) will live by the seashore
    and become a haven for ships;
    his border will extend toward Sidon.(AH)

14 “Issachar(AI) is a rawboned[f] donkey
    lying down among the sheep pens.[g](AJ)
15 When he sees how good is his resting place
    and how pleasant is his land,(AK)
he will bend his shoulder to the burden(AL)
    and submit to forced labor.(AM)

16 “Dan[h](AN) will provide justice for his people
    as one of the tribes of Israel.(AO)
17 Dan(AP) will be a snake by the roadside,
    a viper along the path,(AQ)
that bites the horse’s heels(AR)
    so that its rider tumbles backward.

18 “I look for your deliverance,(AS) Lord.(AT)

19 “Gad[i](AU) will be attacked by a band of raiders,
    but he will attack them at their heels.(AV)

20 “Asher’s(AW) food will be rich;(AX)
    he will provide delicacies fit for a king.(AY)

21 “Naphtali(AZ) is a doe set free
    that bears beautiful fawns.[j](BA)

22 “Joseph(BB) is a fruitful vine,(BC)
    a fruitful vine near a spring,
    whose branches(BD) climb over a wall.[k]
23 With bitterness archers attacked him;(BE)
    they shot at him with hostility.(BF)
24 But his bow remained steady,(BG)
    his strong arms(BH) stayed[l] limber,
because of the hand of the Mighty One of Jacob,(BI)
    because of the Shepherd,(BJ) the Rock of Israel,(BK)
25 because of your father’s God,(BL) who helps(BM) you,
    because of the Almighty,[m](BN) who blesses you
with blessings of the skies above,
    blessings of the deep springs below,(BO)
    blessings of the breast(BP) and womb.(BQ)
26 Your father’s blessings are greater
    than the blessings of the ancient mountains,
    than[n] the bounty of the age-old hills.(BR)
Let all these rest on the head of Joseph,(BS)
    on the brow of the prince among[o] his brothers.(BT)

27 “Benjamin(BU) is a ravenous wolf;(BV)
    in the morning he devours the prey,(BW)
    in the evening he divides the plunder.”(BX)

28 All these are the twelve tribes of Israel,(BY) and this is what their father said to them when he blessed them, giving each the blessing(BZ) appropriate to him.

The Death of Jacob

29 Then he gave them these instructions:(CA) “I am about to be gathered to my people.(CB) Bury me with my fathers(CC) in the cave in the field of Ephron the Hittite,(CD) 30 the cave in the field of Machpelah,(CE) near Mamre(CF) in Canaan, which Abraham bought along with the field(CG) as a burial place(CH) from Ephron the Hittite. 31 There Abraham(CI) and his wife Sarah(CJ) were buried, there Isaac and his wife Rebekah(CK) were buried, and there I buried Leah.(CL) 32 The field and the cave in it were bought from the Hittites.[p](CM)

33 When Jacob had finished giving instructions to his sons, he drew his feet up into the bed, breathed his last and was gathered to his people.(CN)

Footnotes

  1. Genesis 49:5 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  2. Genesis 49:8 Judah sounds like and may be derived from the Hebrew for praise.
  3. Genesis 49:10 Or from his descendants
  4. Genesis 49:10 Or to whom tribute belongs; the meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.
  5. Genesis 49:12 Or will be dull from wine, / his teeth white from milk
  6. Genesis 49:14 Or strong
  7. Genesis 49:14 Or the campfires; or the saddlebags
  8. Genesis 49:16 Dan here means he provides justice.
  9. Genesis 49:19 Gad sounds like the Hebrew for attack and also for band of raiders.
  10. Genesis 49:21 Or free; / he utters beautiful words
  11. Genesis 49:22 Or Joseph is a wild colt, / a wild colt near a spring, / a wild donkey on a terraced hill
  12. Genesis 49:24 Or archers will attack … will shoot … will remain … will stay
  13. Genesis 49:25 Hebrew Shaddai
  14. Genesis 49:26 Or of my progenitors, / as great as
  15. Genesis 49:26 Or of the one separated from
  16. Genesis 49:32 Or the descendants of Heth