Add parallel Print Page Options

29 (A)Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia,
    pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá;
láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀
    yóò ti hù jáde,
    èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko,
    àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu.
Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun,
    yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.

31 Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, Ìwọ ìlú!
    Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia!
Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá,
    kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.

Read full chapter

29 Do not rejoice, all you Philistines,(A)
    that the rod that struck you is broken;
from the root of that snake will spring up a viper,(B)
    its fruit will be a darting, venomous serpent.(C)
30 The poorest of the poor will find pasture,
    and the needy(D) will lie down in safety.(E)
But your root I will destroy by famine;(F)
    it will slay(G) your survivors.(H)

31 Wail,(I) you gate!(J) Howl, you city!
    Melt away, all you Philistines!(K)
A cloud of smoke comes from the north,(L)
    and there is not a straggler in its ranks.(M)

Read full chapter

Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí àwọn ará Filistini

47 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tó tọ wòlíì Jeremiah wá nípa àwọn Filistini, kí ó tó di pé Farao dojúkọ Gasa:

Báyìí ni Olúwa wí:

“Wo bí omi ti ń ru sókè ní àríwá,
    wọn ó di odò tí ń bo bèbè mọ́lẹ̀.
Wọn kò ní borí ilẹ̀ àti ohun gbogbo tó wà lórí rẹ̀,
    ìlú àti àwọn tó ń gbé nínú wọn.
Àwọn ènìyàn yóò kígbe;
    gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà yóò hu
Nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ìró títẹ̀lé pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin alágbára
    nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ọ̀tá ńlá
àti iye kẹ̀kẹ́ wọn.
    Àwọn baba kò ní lè ran àwọn ọmọ lọ́wọ́;
    ọwọ́ wọn yóò kákò.
Nítorí tí ọjọ́ náà ti pé
    láti pa àwọn Filistini run,
kí a sì mú àwọn tí ó là
    tí ó lè ran Tire àti Sidoni lọ́wọ́ kúrò.
Olúwa ti ṣetán láti pa Filistini run,
    àwọn tí ó kù ní agbègbè Kafitori.
Gasa yóò fá irun orí rẹ̀ nínú ọ̀fọ̀.
    A ó pa Aṣkeloni lẹ́nu mọ́;
ìyókù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀,
    ìwọ yóò ti sá ara rẹ lọ́gbẹ́ pẹ́ tó?

“Ẹ̀yin kígbe, ‘Yé è, idà Olúwa,
    yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò sinmi?
Padà sínú àkọ̀ rẹ;
    sinmi kí o sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.’
Ṣùgbọ́n báwo ni yóò ṣe sinmi,
    nígbà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un,
nígbà tí ó ti pa á láṣẹ
    láti dojúkọ Aṣkeloni àti agbègbè rẹ̀.”

A Message About the Philistines

47 This is the word of the Lord that came to Jeremiah the prophet concerning the Philistines(A) before Pharaoh attacked Gaza:(B)

This is what the Lord says:

“See how the waters are rising in the north;(C)
    they will become an overflowing torrent.
They will overflow the land and everything in it,
    the towns and those who live in them.
The people will cry out;
    all who dwell in the land will wail(D)
at the sound of the hooves of galloping steeds,
    at the noise of enemy chariots(E)
    and the rumble of their wheels.
Parents will not turn to help their children;
    their hands will hang limp.(F)
For the day has come
    to destroy all the Philistines
and to remove all survivors
    who could help Tyre(G) and Sidon.(H)
The Lord is about to destroy the Philistines,(I)
    the remnant from the coasts of Caphtor.[a](J)
Gaza will shave(K) her head in mourning;
    Ashkelon(L) will be silenced.
You remnant on the plain,
    how long will you cut(M) yourselves?

“‘Alas, sword(N) of the Lord,
    how long till you rest?
Return to your sheath;
    cease and be still.’(O)
But how can it rest
    when the Lord has commanded it,
when he has ordered it
    to attack Ashkelon and the coast?”(P)

Footnotes

  1. Jeremiah 47:4 That is, Crete

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Filistia

15 (A)“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run, 16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run. 17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.’ ”

Read full chapter

A Prophecy Against Philistia

15 “This is what the Sovereign Lord says: ‘Because the Philistines(A) acted in vengeance and took revenge with malice(B) in their hearts, and with ancient hostility sought to destroy Judah, 16 therefore this is what the Sovereign Lord says: I am about to stretch out my hand against the Philistines,(C) and I will wipe out the Kerethites(D) and destroy those remaining along the coast.(E) 17 I will carry out great vengeance(F) on them and punish(G) them in my wrath. Then they will know that I am the Lord,(H) when I take vengeance on them.(I)’”

Read full chapter

(A)“Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín. Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín. Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.

“Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín. Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.

Read full chapter

“Now what have you against me, Tyre and Sidon(A) and all you regions of Philistia?(B) Are you repaying me for something I have done? If you are paying me back, I will swiftly and speedily return on your own heads what you have done.(C) For you took my silver and my gold and carried off my finest treasures to your temples.[a](D) You sold the people of Judah and Jerusalem to the Greeks,(E) that you might send them far from their homeland.

“See, I am going to rouse them out of the places to which you sold them,(F) and I will return(G) on your own heads what you have done. I will sell your sons(H) and daughters to the people of Judah,(I) and they will sell them to the Sabeans,(J) a nation far away.” The Lord has spoken.(K)

Read full chapter

Footnotes

  1. Joel 3:5 Or palaces

Ìlòdì sí Filistia

(A)Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,
    Aṣkeloni yóò sì dahoro.
Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,
    a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,
    ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;
Ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,
    ilẹ̀ àwọn ara Filistini.
“Èmi yóò pa yín run,
    ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,
    ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,
    níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran,
Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò
    dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,
    yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.

Read full chapter

Philistia

Gaza(A) will be abandoned
    and Ashkelon(B) left in ruins.
At midday Ashdod will be emptied
    and Ekron uprooted.
Woe to you who live by the sea,
    you Kerethite(C) people;
the word of the Lord is against you,(D)
    Canaan, land of the Philistines.
He says, “I will destroy you,
    and none will be left.”(E)
The land by the sea will become pastures
    having wells for shepherds
    and pens for flocks.(F)
That land will belong
    to the remnant(G) of the people of Judah;
    there they will find pasture.
In the evening they will lie down
    in the houses of Ashkelon.
The Lord their God will care for them;
    he will restore their fortunes.[a](H)

Read full chapter

Footnotes

  1. Zephaniah 2:7 Or will bring back their captives

Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù;
    Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi,
    àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í.
Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀,
    Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu,
    Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀,
    àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀:
ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa,
    wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda,
    àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.

Read full chapter

Ashkelon(A) will see it and fear;
    Gaza will writhe in agony,
    and Ekron too, for her hope will wither.
Gaza will lose her king
    and Ashkelon will be deserted.
A mongrel people will occupy Ashdod,
    and I will put an end(B) to the pride of the Philistines.
I will take the blood from their mouths,
    the forbidden food from between their teeth.
Those who are left will belong to our God(C)
    and become a clan in Judah,
    and Ekron will be like the Jebusites.(D)

Read full chapter