Add parallel Print Page Options

Ìtùnú fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run

40 Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú,
    ni Ọlọ́run yín wí.
Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu
    kí o sì kéde fún un
pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí,
    pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,
pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa
    ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

(A)Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù:
    “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe,
    ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
(B)Gbogbo Àfonífojì ni a ó gbé sókè,
    gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀;
wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti
    ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ,
Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀
    gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i.
    Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”

(C)Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.”
    Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?”

“Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko,
    àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,
    nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n.
    Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”

(D)Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni,
    lọ sí orí òkè gíga.
Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu,
    gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo,
gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù;
    sọ fún àwọn ìlú u Juda,
    “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
10 (E)Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára,
    apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un.
Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
    àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
11 Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn:
    Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀.
Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀;
    ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.

12 Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀,
    tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀
tí ó wọn àwọn ọ̀run?
    Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀,
tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n
    àti òkè kéékèèkéé nínú òṣùwọ̀n?
13 (F)Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa,
    tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ
    àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́?
Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n
    tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?

15 Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi
    nínú garawa;
a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n;
    ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
16 Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná,
    tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
17 Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí;
    gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò
    tí kò tó ohun tí kò sí.

18 Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé?
    Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á,
    ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó
    tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
20 Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú
    irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá,
wá igi tí kò le è rà.
    Ó wá oníṣọ̀nà tí ó
    láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.

21 Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀
    ìwọ kò tí ì gbọ́?
A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá?
    Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
22 Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé,
    àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata.
Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà,
    ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
23 Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán
    àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
24 Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n,
    kété tí a gbìn wọ́n,
kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ,
    bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.

25 “Ta ni ẹ ó fi mi wé?
    Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
26 Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run:
    Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí?
Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan
    tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan.
Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀,
    ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.

27 Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu
    àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli;
“Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa;
    ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí
    láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
28 Ìwọ kò tí ì mọ̀?
    Ìwọ kò tí ì gbọ́?
Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé,
    Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé.
Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀,
    àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
29 Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀
    ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
30 Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì,
    àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
31 ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa
    yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun.
Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì;
    wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn,
    wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.

Comfort for God’s People

40 Comfort, comfort(A) my people,
    says your God.
Speak tenderly(B) to Jerusalem,
    and proclaim to her
that her hard service(C) has been completed,(D)
    that her sin has been paid for,(E)
that she has received from the Lord’s hand
    double(F) for all her sins.

A voice of one calling:
“In the wilderness prepare
    the way(G) for the Lord[a];
make straight(H) in the desert
    a highway for our God.[b](I)
Every valley shall be raised up,(J)
    every mountain and hill(K) made low;
the rough ground shall become level,(L)
    the rugged places a plain.
And the glory(M) of the Lord will be revealed,
    and all people will see it together.(N)
For the mouth of the Lord has spoken.”(O)

A voice says, “Cry out.”
    And I said, “What shall I cry?”

“All people are like grass,(P)
    and all their faithfulness is like the flowers of the field.
The grass withers(Q) and the flowers fall,
    because the breath(R) of the Lord blows(S) on them.
    Surely the people are grass.
The grass withers and the flowers(T) fall,
    but the word(U) of our God endures(V) forever.(W)

You who bring good news(X) to Zion,
    go up on a high mountain.
You who bring good news to Jerusalem,[c](Y)
    lift up your voice with a shout,
lift it up, do not be afraid;
    say to the towns of Judah,
    “Here is your God!”(Z)
10 See, the Sovereign Lord comes(AA) with power,(AB)
    and he rules(AC) with a mighty arm.(AD)
See, his reward(AE) is with him,
    and his recompense accompanies him.
11 He tends his flock like a shepherd:(AF)
    He gathers the lambs in his arms(AG)
and carries them close to his heart;(AH)
    he gently leads(AI) those that have young.(AJ)

12 Who has measured the waters(AK) in the hollow of his hand,(AL)
    or with the breadth of his hand marked off the heavens?(AM)
Who has held the dust of the earth in a basket,
    or weighed the mountains on the scales
    and the hills in a balance?(AN)
13 Who can fathom the Spirit[d](AO) of the Lord,
    or instruct the Lord as his counselor?(AP)
14 Whom did the Lord consult to enlighten him,
    and who taught him the right way?
Who was it that taught him knowledge,(AQ)
    or showed him the path of understanding?(AR)

15 Surely the nations are like a drop in a bucket;
    they are regarded as dust on the scales;(AS)
    he weighs the islands as though they were fine dust.(AT)
16 Lebanon(AU) is not sufficient for altar fires,
    nor its animals(AV) enough for burnt offerings.
17 Before him all the nations(AW) are as nothing;(AX)
    they are regarded by him as worthless
    and less than nothing.(AY)

18 With whom, then, will you compare God?(AZ)
    To what image(BA) will you liken him?
19 As for an idol,(BB) a metalworker casts it,
    and a goldsmith(BC) overlays it with gold(BD)
    and fashions silver chains for it.
20 A person too poor to present such an offering
    selects wood(BE) that will not rot;
they look for a skilled worker
    to set up an idol(BF) that will not topple.(BG)

21 Do you not know?
    Have you not heard?(BH)
Has it not been told(BI) you from the beginning?(BJ)
    Have you not understood(BK) since the earth was founded?(BL)
22 He sits enthroned(BM) above the circle of the earth,
    and its people are like grasshoppers.(BN)
He stretches out the heavens(BO) like a canopy,(BP)
    and spreads them out like a tent(BQ) to live in.(BR)
23 He brings princes(BS) to naught
    and reduces the rulers of this world to nothing.(BT)
24 No sooner are they planted,
    no sooner are they sown,
    no sooner do they take root(BU) in the ground,
than he blows(BV) on them and they wither,(BW)
    and a whirlwind sweeps them away like chaff.(BX)

25 “To whom will you compare me?(BY)
    Or who is my equal?” says the Holy One.(BZ)
26 Lift up your eyes and look to the heavens:(CA)
    Who created(CB) all these?
He who brings out the starry host(CC) one by one
    and calls forth each of them by name.
Because of his great power and mighty strength,(CD)
    not one of them is missing.(CE)

27 Why do you complain, Jacob?
    Why do you say, Israel,
“My way is hidden from the Lord;
    my cause is disregarded by my God”?(CF)
28 Do you not know?
    Have you not heard?(CG)
The Lord is the everlasting(CH) God,
    the Creator(CI) of the ends of the earth.(CJ)
He will not grow tired or weary,(CK)
    and his understanding no one can fathom.(CL)
29 He gives strength(CM) to the weary(CN)
    and increases the power of the weak.
30 Even youths grow tired and weary,
    and young men(CO) stumble and fall;(CP)
31 but those who hope(CQ) in the Lord
    will renew their strength.(CR)
They will soar on wings like eagles;(CS)
    they will run and not grow weary,
    they will walk and not be faint.(CT)

Footnotes

  1. Isaiah 40:3 Or A voice of one calling in the wilderness: / “Prepare the way for the Lord
  2. Isaiah 40:3 Hebrew; Septuagint make straight the paths of our God
  3. Isaiah 40:9 Or Zion, bringer of good news, / go up on a high mountain. / Jerusalem, bringer of good news
  4. Isaiah 40:13 Or mind