Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ àti ìgbàlà

65 (A)“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi;
    Àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi.
Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi,
    Ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta
    sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle,
tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára,
    tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo
    lójú ara mi gan an,
wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà
    wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
wọ́n ń jókòó láàrín ibojì
    wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀;
tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,
    tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi,
    nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’
Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi
    iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.

“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi:
    Èmi kì yóò dákẹ́,
ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́;
    Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá
    wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré,
Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn
    ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

Báyìí ni Olúwa wí:

“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà
    tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,
nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’
    bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;
    Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu,
    àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì;
àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,
    ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
10 Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,
    àti Àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,
    fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11 “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀
    tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi,
tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi
    tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
12 Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà,
    àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa;
nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn.
    Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀
Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi
    ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”

13 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;
    ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,
àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,
    ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;
àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,
    ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
14 Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin
    láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,
ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè
    láti inú ìrora ọkàn yín
    àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
15 Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀
    fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún;
Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín,
    ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun
    yóò fún ní orúkọ mìíràn
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà
    yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;
Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà
    yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.
Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé
    yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.

Àwọn ọrun tuntun àti ayé tuntun

17 “Kíyèsi i, Èmi yóò dá
    àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun
A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,
    tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
18 Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé
    nínú ohun tí èmi yóò dá,
nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú
    àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
19 Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu
    n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi;
ariwo ẹkún àti igbe
    ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.

20 “Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀
    ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀,
tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán;
    ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún
ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé;
    ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan
    ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
21 Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn
    wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
22 Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé,
    tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ,
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan,
    bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí;
àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́
    wọn fún ìgbà pípẹ́.
23 Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán,
    wọn kí yóò bímọ fún wàhálà;
    nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún,
    àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
24 Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;
    nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
25 (B)Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀,
    kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù,
ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò.
    Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run
ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”
    ni Olúwa wí.

Judgment and Salvation

65 “I revealed myself to those who did not ask for me;
    I was found by those who did not seek me.(A)
To a nation(B) that did not call on my name,(C)
    I said, ‘Here am I, here am I.’
All day long I have held out my hands
    to an obstinate people,(D)
who walk in ways not good,
    pursuing their own imaginations(E)
a people who continually provoke me
    to my very face,(F)
offering sacrifices in gardens(G)
    and burning incense(H) on altars of brick;
who sit among the graves(I)
    and spend their nights keeping secret vigil;
who eat the flesh of pigs,(J)
    and whose pots hold broth of impure meat;
who say, ‘Keep away; don’t come near me,
    for I am too sacred(K) for you!’
Such people are smoke(L) in my nostrils,
    a fire that keeps burning all day.

“See, it stands written before me:
    I will not keep silent(M) but will pay back(N) in full;
    I will pay it back into their laps(O)
both your sins(P) and the sins of your ancestors,”(Q)
    says the Lord.
“Because they burned sacrifices on the mountains
    and defied me on the hills,(R)
I will measure into their laps
    the full payment(S) for their former deeds.”

This is what the Lord says:

“As when juice is still found in a cluster of grapes(T)
    and people say, ‘Don’t destroy it,
    there is still a blessing in it,’
so will I do in behalf of my servants;(U)
    I will not destroy them all.
I will bring forth descendants(V) from Jacob,
    and from Judah those who will possess(W) my mountains;
my chosen(X) people will inherit them,
    and there will my servants live.(Y)
10 Sharon(Z) will become a pasture for flocks,(AA)
    and the Valley of Achor(AB) a resting place for herds,
    for my people who seek(AC) me.

11 “But as for you who forsake(AD) the Lord
    and forget my holy mountain,(AE)
who spread a table for Fortune
    and fill bowls of mixed wine(AF) for Destiny,
12 I will destine you for the sword,(AG)
    and all of you will fall in the slaughter;(AH)
for I called but you did not answer,(AI)
    I spoke but you did not listen.(AJ)
You did evil in my sight
    and chose what displeases me.”(AK)

13 Therefore this is what the Sovereign Lord says:

“My servants will eat,(AL)
    but you will go hungry;(AM)
my servants will drink,(AN)
    but you will go thirsty;(AO)
my servants will rejoice,(AP)
    but you will be put to shame.(AQ)
14 My servants will sing(AR)
    out of the joy of their hearts,
but you will cry out(AS)
    from anguish of heart
    and wail in brokenness of spirit.
15 You will leave your name
    for my chosen ones to use in their curses;(AT)
the Sovereign Lord will put you to death,
    but to his servants he will give another name.(AU)
16 Whoever invokes a blessing(AV) in the land
    will do so by the one true God;(AW)
whoever takes an oath in the land
    will swear(AX) by the one true God.
For the past troubles(AY) will be forgotten
    and hidden from my eyes.

New Heavens and a New Earth

17 “See, I will create
    new heavens and a new earth.(AZ)
The former things will not be remembered,(BA)
    nor will they come to mind.
18 But be glad and rejoice(BB) forever
    in what I will create,
for I will create Jerusalem(BC) to be a delight
    and its people a joy.
19 I will rejoice(BD) over Jerusalem
    and take delight(BE) in my people;
the sound of weeping and of crying(BF)
    will be heard in it no more.

20 “Never again will there be in it
    an infant(BG) who lives but a few days,
    or an old man who does not live out his years;(BH)
the one who dies at a hundred
    will be thought a mere child;
the one who fails to reach[a] a hundred
    will be considered accursed.
21 They will build houses(BI) and dwell in them;
    they will plant vineyards and eat their fruit.(BJ)
22 No longer will they build houses and others live in them,(BK)
    or plant and others eat.
For as the days of a tree,(BL)
    so will be the days(BM) of my people;
my chosen(BN) ones will long enjoy
    the work of their hands.
23 They will not labor in vain,(BO)
    nor will they bear children doomed to misfortune;(BP)
for they will be a people blessed(BQ) by the Lord,
    they and their descendants(BR) with them.
24 Before they call(BS) I will answer;(BT)
    while they are still speaking(BU) I will hear.
25 The wolf and the lamb(BV) will feed together,
    and the lion will eat straw like the ox,(BW)
    and dust will be the serpent’s(BX) food.
They will neither harm nor destroy
    on all my holy mountain,”(BY)
says the Lord.

Footnotes

  1. Isaiah 65:20 Or the sinner who reaches