Jeremiah 49:1-6
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Ammoni
49 (A)Ní ti Ammoni:
Báyìí ni Olúwa wí:
“Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin?
Israẹli kò ha ní àrólé bí?
Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi?
Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,”
ni Olúwa wí;
“nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba
tí Ammoni yóò sì di òkìtì ahoro,
gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná.
Nígbà náà ni Israẹli yóò
lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,”
ni Olúwa wí.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni
nítorí Ai tí rún,
kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba!
Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀.
Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà,
nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn
pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú Àfonífojì rẹ,
ṣògo nínú Àfonífojì rẹ fún èso?
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́,
ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé,
‘ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ
láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,”
ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan
tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,”
ni Olúwa wí.
Jeremiah 49:1-6
New International Version
A Message About Ammon
49 Concerning the Ammonites:(A)
This is what the Lord says:
“Has Israel no sons?
Has Israel no heir?
Why then has Molek[a](B) taken possession of Gad?(C)
Why do his people live in its towns?
2 But the days are coming,”
declares the Lord,
“when I will sound the battle cry(D)
against Rabbah(E) of the Ammonites;
it will become a mound of ruins,(F)
and its surrounding villages will be set on fire.
Then Israel will drive out
those who drove her out,(G)”
says the Lord.
3 “Wail, Heshbon,(H) for Ai(I) is destroyed!
Cry out, you inhabitants of Rabbah!
Put on sackcloth(J) and mourn;
rush here and there inside the walls,
for Molek(K) will go into exile,(L)
together with his priests and officials.
4 Why do you boast of your valleys,
boast of your valleys so fruitful?
Unfaithful Daughter Ammon,(M)
you trust in your riches(N) and say,
‘Who will attack me?’(O)
5 I will bring terror on you
from all those around you,”
declares the Lord, the Lord Almighty.
“Every one of you will be driven away,
and no one will gather the fugitives.(P)
6 “Yet afterward, I will restore(Q) the fortunes of the Ammonites,”
declares the Lord.
Footnotes
- Jeremiah 49:1 Or their king; also in verse 3
Esekiẹli 21:28-32
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
28 (A)“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn:
“ ‘Idà kan idà kan
tí á fa yọ fún ìpànìyàn
tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò
àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín
àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín
a yóò gbé e lé àwọn ọrùn
ènìyàn búburú ti a ó pa,
àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé,
àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
30 “ ‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀
Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín,
ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín,
èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná
mi bá yín jà.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà,
a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín,
a kì yóò rántí yín mọ́;
nítorí èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’ ”
Ezekiel 21:28-32
New International Version
28 “And you, son of man, prophesy and say, ‘This is what the Sovereign Lord says about the Ammonites(A) and their insults:
“‘A sword,(B) a sword,
drawn for the slaughter,
polished to consume
and to flash like lightning!
29 Despite false visions concerning you
and lying divinations(C) about you,
it will be laid on the necks
of the wicked who are to be slain,
whose day has come,
whose time of punishment has reached its climax.(D)
30 “‘Let the sword return to its sheath.(E)
In the place where you were created,
in the land of your ancestry,(F)
I will judge you.
31 I will pour out my wrath on you
and breathe(G) out my fiery anger(H) against you;
I will deliver you into the hands of brutal men,
men skilled in destruction.(I)
32 You will be fuel for the fire,(J)
your blood will be shed in your land,
you will be remembered(K) no more;
for I the Lord have spoken.’”
Esekiẹli 25:1-7
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Ammoni
25 (A)Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: 2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn. 3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé: Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn, 4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ: wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ. 5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. 6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli 7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”
Read full chapter
Ezekiel 25:1-7
New International Version
A Prophecy Against Ammon
25 The word of the Lord came to me: 2 “Son of man, set your face against(A) the Ammonites(B) and prophesy against them.(C) 3 Say to them, ‘Hear the word of the Sovereign Lord. This is what the Sovereign Lord says: Because you said “Aha!(D)” over my sanctuary when it was desecrated(E) and over the land of Israel when it was laid waste and over the people of Judah when they went into exile,(F) 4 therefore I am going to give you to the people of the East(G) as a possession. They will set up their camps(H) and pitch their tents among you; they will eat your fruit and drink your milk.(I) 5 I will turn Rabbah(J) into a pasture for camels and Ammon into a resting place for sheep.(K) Then you will know that I am the Lord. 6 For this is what the Sovereign Lord says: Because you have clapped your hands(L) and stamped your feet, rejoicing with all the malice of your heart against the land of Israel,(M) 7 therefore I will stretch out my hand(N) against you and give you as plunder(O) to the nations. I will wipe you out from among the nations and exterminate you from the countries. I will destroy(P) you, and you will know that I am the Lord.(Q)’”
Sefaniah 2:8-11
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni
8 (A)“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9 Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
“nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
ibi tí ó kún fún yèrèpè
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni
yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
Zephaniah 2:8-11
New International Version
Moab and Ammon
8 “I have heard the insults(A) of Moab(B)
and the taunts of the Ammonites,(C)
who insulted(D) my people
and made threats against their land.(E)
9 Therefore, as surely as I live,”
declares the Lord Almighty,
the God of Israel,
“surely Moab(F) will become like Sodom,(G)
the Ammonites(H) like Gomorrah—
a place of weeds and salt pits,
a wasteland forever.
The remnant of my people will plunder(I) them;
the survivors(J) of my nation will inherit their land.(K)”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.