Jeremiah 6:25
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá
tàbí kí o máa rìn ní àwọn
ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà,
ìpayà sì wà níbi gbogbo.
Jeremiah 20:3
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
3 (A)Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
Read full chapter
Jeremiah 20:10
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
10 Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́,
ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo
Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn!
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró
kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé,
Bóyá yóò jẹ́ di títàn,
nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀,
àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
Jeremiah 46:5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
5 (A)Kí ni nǹkan tí mo tún rí?
Wọ́n bẹ̀rù,
wọ́n sì ń padà sẹ́yìn,
wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun.
Wọ́n sá,
wọn kò sì bojú wẹ̀yìn,
ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,”
ni Olúwa wí.
Saamu 31:13
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
13 (A)Nítorí mo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpayà tí ó yí mi ká;
tí wọn gbìmọ̀ pọ̀ sí mi,
wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi
láti gba ẹ̀mí mi.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.